Ayédèrú agbẹjọ́rò tó ṣiṣẹ́ fún ọdún mẹ́ta láì ní'wé ẹ̀rí

Ayederu agbejoro

Oríṣun àwòrán, LAGOS STATE POLICE COMMAND

Àkọlé àwòrán, Uche Julian Nwajiakwu bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ agbẹjọ́rò ni 2015

Ọwọ́ ọlọ́pàá ti tẹ arákùnrín kan ní ilé ẹjọ́ ìbílẹ̀ tí ó wà ní Ọ̀jọ́ ni Ìpínlẹ̀ Eko lórí ẹ̀sùn pé ayédèrú agbẹjarò ni.Agbẹnusọ fún àjọ ọlọ́pàá Ìpínlẹ̀ Eko, Chike Oti, sọ wipé àwọn ikọ̀ ọ̀tẹlẹ̀múyẹ́ àjọ náà ni ó mu u, ti ó sì jẹ́wọ́ wípé òun ti ń ṣiṣẹ́ agbẹjọ́rò fún ọdún mẹ́ta láà ní ìwé ẹ̀rí kankan.

Ilé ẹjọ́ kan náà ni Ọ̀jọ́ tí wọn ti mú arákùnrín náà ni awọn ọlọ́pàá gbé e lọ láti lọ jẹ́jọ́.

Ajọ ọlọ́pàá nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò rẹ̀, ayédèrú agbẹjarò náà ní òun nífẹ̀ sí ìṣẹ́ agbẹjọ́rò nígbà tí ọ̀rẹ́ rẹ̀ kan ran kí ó ṣe bí amòfin láti lọ jáwè fún ayálégbé kan.

A gbọ́ pé ọwọ́ tẹ̀ ẹ́ nígbà tí àwọn ojúlówó agbẹjọ́rò tó wà nínu ilé ẹjọ́ nígbà tí ó ń sọrọ níwájú adájọ funra pé kò kàwé.