Ẹgbẹ̀rúndínlàádọ́ta àwọn Agbéṣùmọ̀mí láti ṣekúpa láàrín oṣù méje- Iléeṣẹ́ ológun Nàìjírà

Oríṣun àwòrán, @Nig Army
Àjọ ọmọ ogun orílẹ̀ èdè yìí ti ní kò dín ní Ẹgbẹ̀rúndínlàádọ́ta àwọn Agbéṣùmọ̀mí tí àwọn ti rán sọ́run láàárín oṣù Òkùkú 2021 sí oṣù Ṣẹrẹ 2022.
Bákan náà ni wọ́n ní àwọn Agbébọnjà ọ̀jìlélẹ́ẹ̀dẹ́gbẹ̀tadínmẹ́ta ní àwọn ti yọwọ́ wọn kúrò láwo.
Àwọn wọ̀nyìí kò yọ àwọn èèkàn nínú iṣẹ́ láabi ọ̀hún tó fi mọ́ àwọn Emir kan àti àwọn olórí Agbébọnjà méjì ní ìpínlẹ̀ Zamfara, Alhaji Auta àti Kachala Ruga.
- Lásìkò ìséde Covid 19, wo bí àwọn olùgbé ìlú yí ṣé n fí fóónù ṣé pàṣípààrọ̀ oúnjẹ
- Obìnrin kan ń pa ẹgbèrún méjìdínlógójì Pọ́ùn lọ́sẹ̀ fún isó títa
- Ka nípa àwọn Fásìtì 25 péré tí àjọ NUC ní ètò ẹ̀kọ́ wọ́n kájúẹ̀ ní Nàìjíríà
- Àrà mérìírí! Ìbejí tí a bí ní ọdun 2021 àti 2022 pẹ̀lú ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀dògún láàrin wọn
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti wẹ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún àti òṣìṣẹ́ márùn-ún ilé ẹ̀kọ́ Dowen College mọ́
- Inú wa dún pé Oba Oke dá ẹ̀mí Iyabo Oko padà, a gbàgbọ́ pé ìya wa ṣì máa gbádùn pẹ̀lú àdúrà- Omo Iyabo Oko
Aṣojú Adarí ẹ̀ka ètò ìròyìn,Ogagaun agba Benard Onyeuko lo ṣíṣọ lójú ọ̀rọ̀ ọ̀hú ní ìlú Abuja nígbà tó ń bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀.
Ogagun agba Benard Onyeuko fi kun pé ẹgbẹ̀rún kan àwọn ènìyàn tó wà ní àhámọ́ pẹ̀lú àwọn ohun ìjà ni wọn rí gbà.
Ó sọ síwájú pé mọ́kàndínlọ́gọ́rin Agbéṣùmọ̀mí ni ó ti wà ní láàárín àkókò yìí.










