Obìnrin kan ń pa ẹgbèrún méjìdínlógójì Pọ́ùn lọ́sẹ̀ fún isó títa

Oríṣun àwòrán, Others
Stephaine Matto nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí iṣẹ́ àràmàǹdà tó yàn láàyò ẹgbẹ̀rún kan dọ́là ni òun ń ta ìgò isó kan.
Ó ṣàlàyé pé ọ̀pọ̀ ènìyàn tó ń tẹ̀lé òun lórí orí ẹ̀rọ ayélujára fún òun ní àǹfààní láti ní oníbàárà púpọ̀.
Stepahine Matto fi kun pé òun ń ta àádọ́ta ìgò isó lọ́sẹ̀ kan.
- Lẹ́yìn wákàtí mẹ́ta tí wọ́n kéde pé ìyá mi kú, ó tún mi ọwọ́ rẹ̀ ooo - Ọmọ Iyabo Oko
- Àrà mérìírí! Ìbejí tí a bí ní ọdun 2021 àti 2022 pẹ̀lú ìṣẹ́jú mẹ́ẹ̀dògún láàrin wọn
- Ta ni Oloye Lekan Balogun tí àwọn Ìgbìmọ̀ Afọbajẹ Ibadan fẹnukò pé òun ni Olubadan ilẹ̀ Ibadan kàn?
- Afenifere, PDP, Ohaneze sọ̀kò ọ̀rọ̀ sí Buhari lórí ọ̀rọ̀ tó sọ nípa ètò ààbò
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Èkó ti wẹ àwọn akẹ́kọ̀ọ́ márùn-ún àti òṣìṣẹ́ márùn-ún ilé ẹ̀kọ́ Dowen College mọ́
Ẹwẹ̀, Stephaine ṣeéṣe kí isó tí ó ti fún kúrò lára pọ̀ púpọ̀ jù bí ó ṣe yẹ lo fi di èrò ilé ìwòsàn.
Ó ní ọ̀pọ̀ ẹ̀wà ni òun jẹ kí òun lè bá à máa rí isó ya ṣùgbọ́n ó ṣe àkóbá fún èèmí òun tí òun rò wí pé òun ti ní síròkì to jẹ arun rọpa rọsẹ.
Dókítà ti ní kí ó pààrọ̀ òunjẹ rẹ̀ báyìí kí àlááfìà le ba Stephaine.
Stephaine Matto ní ohun tí dókítà tí mú òpin bá iṣẹ́ òun ìpinnu tó dùn mọ́ àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀.










