Sowore: Èèyàn márùn ùn láwọn tó pa àbúrò Sowore jígbé- iléeṣẹ́ ọlọ́pàá

Oríṣun àwòrán, Others
Ileeṣẹ ọlọpaa ti sọ pe lootọ lawọn ajinigbe kan ṣeku pa aburo gbajugbaja ajafẹtọmọniyan Omoyele Sowore.
Ninu ọrọ ti a ri lọdọ ileeṣẹ iroyin Naijiria Daily Trust,alukoro awọn ọlọpaa ni ipinlẹ Edo Bello Kontongs ni afurasi ajinigbe lo yinbọn pa Felix Olajide.
Bello ni lagbegbe Isuwa lopopona marose Lagos-Benin ni wọn ti yinbọn pa ni nkan bi ago meje ku diẹ lowurọ.
Gẹgẹ bi ileeṣẹ iwe iroyin naa ṣe sọ,awọn ọlọpaa ni wọn tun ji eeyan marun un mii gbe.
Wọn tẹsiwaju pe wọn ti gbe oku Felix lọ si aaye igbokupamọsi fasiti Igbinedion to wa ni Okada.
Ọlọpaa wa fi kun pe iwadii n tẹsiwaju lati le fi doola awọn eeyan marun un ti wọn ji gbe.

Oríṣun àwòrán, Others
Ajafẹtọ ọmọniyan, Omọyẹle Sowore ti ṣedaro aburo re Olajide ti o pade iku ojiji ni opopona Benin-ore, ni agbegbe Okada, nipinlẹ Edo.
Ninu atẹjade ti Sowore fi si oju opo Facebook rẹ lo ti kerora iku to mu aburo rẹ lọ.
Sowore ni awọn darandaran ajinigbe lo ṣekọlu si aburo oun lasiko to n bọ lati fasiti Igbinedion nibi to ti n kọ iṣẹ apoogun, ki awọn ẹni ibi naa to ṣekupa a.
- Graphology: Àǹfààní márùn-ún tó wá nínú ìmọ̀ nípa 'Handwriting' rẹ
- Ìjọba dá àwọn Kristẹni tó ń rìnrìnàjò lọ sí Isreal padà nítorí abẹ́rẹ́ ajẹsára Covid-19
- Wo ohun márùn-ún tó ń fa kí nǹkan ọkùnrin má le
- DSS tú èèyàn méjì míì silẹ nínú àmúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ Sunday Igboho mẹ́rin tó kù sí àhámọ́ rẹ
- Yoruba Nation kọ́ ni ọ̀nà àbáyọ sí ìṣòro Naijiria, ìlànà àtúntò ni - Deji ti Akure
- Ìyà, ìṣẹ́ pọ̀! ó kéré tán 27.4M ọmọ Naijiria ní kò rí N100,000 ní ọdún - SERAP
- Ọmọ ẹgbẹ́ Boko Haram 6,000 ti jọ́wọ̀ ara wọn fún ìjọba Naijiria
''Wọn ti gba ẹmi lẹnu ọmọ eniyan miran, sun ninu agbara dokita Mamiye!

Oríṣun àwòrán, Others
''Gbogbo iwa ọdaran yoo jẹ ki idajọ awọn eniyan yii tete de ni kiakia ni''
''Emi ati iwọ ni a ma n tẹle baba wa jade nigba ti a wa ni kekere, ti o si jẹ ọmọ to nifẹ ti ko si lọta''
''Ohun gbogbo to o ṣe ni lati jẹki inu awọn to wa ni ayika rẹ dun ni gbogbo igba.''
Ajafẹtọ ọmọniyan, Omọyẹle Sowore ni aburo oun ṣiṣẹ lati jẹ ki gbogbo awọn to wa ni agbegbe rẹ wa ni alaafia, amọ iku ati ohun gbogbo ti ko dara mu ẹmi rẹ lọ ni ọsan gangan.
Sowore ṣe apejuwe ọjọ iku aburo rẹ gẹgẹ bi ọjọ ibanujẹ to gajulọ.
- Àwọn jàndùkú tún ṣọṣẹ́ ní Zamfara, wọ́n pa ọlọ́pàá kan àti olórí fijilanté
- Àìsàn wo ló ń bá Okele, òṣèré tíátà finra, tó fi dèrò ilé ìwòsàn?
- Á ṣiṣẹ́ tako Seyi Makinde fún sáà kejì - Igun PDP l‘Oyo fọnmú
- Wàhálà lẹ̀ ń wá tẹ́ ẹ̀ bá tú Sunday Igboho àtàwọn èèyàn rẹ̀ mẹ́rin sílẹ̀ ní àhámọ́ - Ọmọ Nàíjíríà lókè òkun
- "Ọmọ Naijiria, ẹ dúpẹ́ lọ́wọ́ Elédùà tó fi ìjọba Buhari ta wá lọ́rẹ''
- Ẹ wo àtúpalẹ̀ bí Bobrisky ṣe ná ₦500m péré láti ṣe ọjọ́ ìbí
Bakan naa ni awọn ololufẹ rẹ loju opo ikansiraẹni Facebook ti bẹrẹ si ni fi ọrọ ikẹdun ranṣẹ si, ti wọn n ki ku ọrọ ẹni ire to lọ.
Ọmọyele Sowore ati awọn ẹbi rẹ wa lati ijọba ibilẹ Ese-odo ni ipinlẹ Ondo.
















