Buhari: Adesina ní táwọn ọmọ Naijiria bá mọ oore, ó yẹ kí wọn yin Ọlọ́run pé nǹkan ń dára si lórí ètò ààbò

Buhari

Oríṣun àwòrán, Others

Oludamọran fun Aarẹ Buhari lori ọrọ iroyin, Femi Adesina ti sọ idi ti awọn ọmọ Naijiria fi gbọdọ dupẹ lọwọ Ọlọrun fun ijọba aarẹ Buhari lori ọrọ aabo.

Adesina to sọrọ yii lori eto Channels TV ni igbagbọ oun ni pe ọpọlọpọ nnkan lo dara si, labẹ iṣejọba aarẹ Buhari.

O ni bio tilẹ jepe ọrọ aabo to mẹhẹ peleke si ni awọn ibi kan, amọ a ko si ni ibi ti a wa nigba kan ri.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

''Ti a ba mọ oore ni, ti a si jẹ olootọ eniyan, o yẹ ki a wo awọn agbegbe kan lori ọrọ aabo, ki a si dupẹ lọwọ Ọlọrun pe nkan dara si ni awọn agbegbe yii.''

''O ni awọn agbegbe kan ti nkan ti dara ju bi wọn ṣe wa tẹlẹ, bi o tilẹ jẹ pe awọn iṣoro ati idojukọ wa loriṣiriṣi''

Oludamọran fun Aarẹ Buhari lori ọrọ iroyin, Femi Adesina ni o da oun loju pe laipẹ laijina, ki ijọba aarẹ Buhari to pari, ni gbogbo idojukọ ni ẹka eto aabo yoo dopin.

Eleyii ko ṣẹyin bi awọn agbebọn ṣe ṣekọlu si ileewe awọn ọmọde ni ipinlẹ Zamfara, ti wọn si ji ọmọ to le ni aadọta gbe lọ.

Awọ̀ akẹkọọ to joko silẹ

Oríṣun àwòrán, Muhammed Maradun

Bakan naa ni ọpọlọpọ ijinigbe, ipaniyan ni awọn agbebọn ti ṣe si awọn ipinlẹ bii Katsina, Kebbi, Niger, Kaduna ati Zamfara, eleyii to mu ki wọn ti lara awọn ileewe ni agbegbe wọnyii.

Ni iha Guusu Naijiria bakan naa ni ijinigbe n waye, ti awọn afurasi Fulani darandaran ṣi n da wahala silẹ, to fi mọ ijinigbe ati ija pẹlu awọn agbẹ ni awọn agbegbe wọnyii.

Amọ aarẹ Buhari ninu ọrọ rẹ lasiko to n ṣe ifilọlẹ igbimọ adari tuntun fun ajọ idokoowo owoolu, NSIA, ni o di igba ti oun ba ti lọ tan ki awọn ọmọ Naijiria to lee mọ iyi oun.