Muhammadu Buhari: Ààrẹ Buhari ní ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àkànṣe tí òun ṣe yóò lérè lọ́jọ́ iwájú

Oríṣun àwòrán, other
Aarẹ Muhammadu Buhari ti sọ pe o di igba ti oun ba ti lọ tan ki awọn ọmọ Naijiria to lee mọ iyi oun.
Nigba to n sọrọ nilu Abuja lọjọru nigba to n ṣe ifilọlẹ igbimọ adari tuntun fun ajọ idokoowo owoolu, NSIA, aarẹ Buhari ni awọn iṣẹ akanṣe ti iṣejọba oun rawọle jẹ awọn ti yoo mu anfani ọlọjọ gbọọrọ wa fun orilẹede Naijiria.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Buhari ṣíjú àánú wo àádọrin Sọ́jà tó gbọjọ́ ikú, bo ṣe ń dárí jin àwọn Boko Haram tó ronú pìwàdà - Falana
- "Alhaji Fatai, ti DSS pa nílé Sunday Igboho ni kò ríran"
- Wo ìpínlẹ̀ mọ́kànlá tí ìdaranjẹ̀ ti di èèwọ̀ ní gúúsú Nàíjíríà
- UK ya kúrò lára EU, Yorùbá le yapa lára Nàíjíría tí kò bá sí ìwé òfin tuntun - Gbadamosi, Ilana Omo Oodua
- Wo àwọn ọmọ ìgbìmọ̀ ìṣejọba tí Ààrẹ Buhari yọ nípò àti àwọn tó fi rọ́pò wọn
- O ti di èèwọ́ láti ṣẹ̀ oyún lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ mẹ́fà ní ìpínlẹ̀ yìí
- Buhari, àbẹ́rẹ́ àjẹsára kàńpá kọ́ ló kàn bí kò ṣe ko kọ́kọ́ mú ara dẹ ìlú - Aráàlú faraya
Aarẹ wa rọ awọn ọmọ igbimọ ajọ naa lati wa ọna ti orilẹede Naijiria le fi ri anfani ipawo wọle lati ẹka miran yatọ si ẹka epo rọbi nitori afojusun awọn onims nipa epo rọbi ni pe owo epo rọbi lọja agbaye yoo ja walẹ si ogoji dọla lori agba epo rọbi kan nigba ti a o ba fi wọ ọdun 2030.
Nigba to n sọrọ ni tirẹ, minisita feto iṣuna Zainab Ahmed ni owo ti wọn fi bẹrẹ iṣẹ okoowo ni ajọ naa nigba ti aarẹ wọle ni ọdun 2015 jẹ biliọnu kan dọla.
O ni owo naa ti mu ere biliọnu mẹta abọ dọla wọle fun un bayii.













