Boko Haram Geidam Attack: Gómìnà Mai Mala Buni ní inú ìpayínkeke ni èèyàn ìpínlẹ̀ Yobe wà

Oríṣun àwòrán, Mai Mala Buni
Gómìnà ìpínlẹ̀ Yobe Mai Mala Buni, ti fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé, ìpińlẹ̀ oun tí wà ní ipò tó níra lọ́wọ́ ikọ̀ ọmọ ogun Boko Haram, láti ọjọ́ Eti tó kọjá.
Mai Mala ni gbogbo ènìyàn ló mọ gbogbo ǹkan tó n ṣelẹ̀ ní apá ìlà-òòrùn àríwá, sùgbọ́n ó ní èyí tó ń wáyé lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí nílò àbójútó.
Nínú ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú BBC, gómìnà náà sàlàyé pé, nǹkan ṣì sẹ́pẹ́rẹ́ lásìkò díẹ̀ sẹ́yìn, sùgbọ́n lẹ́nù ọjọ́ mẹ́ta yìí, nǹkan ti yíwọ́ nítori pé kò sí ẹni tó mọ nǹkan ti àwọn èniyàn tó wà nídi ìkọlù yìí ń fẹ́.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Agbébọn yabo ilé Sunday Igboho ní òru mọ́jú
- Iyabo Ojo àti Foluke Daramola tako ara wọn lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Ọmọ Nàíjíríà kan kú lásìkò tó bẹ́ sí River Thames ní London torí ó fẹ́ dóòlá ẹ̀mí obìnrin kan
- Buhari ló ń ki àwọn agbésùnmọ̀mí láyà láti ṣe ìkọlù - Ajàfẹ́tọ̀ọ́ẹni
- Ikú Jelili kó lọ lásán, iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ Jonathan ọlọ́pàá tó ṣekúpa ní Quilox
- Ọjọ́ ìsinmi òni ro! Agbébọn ṣé ikọlù sílé ìjọ́sìn ní Kaduna, wọ́n jí ọ̀pọ̀ olùjọ́sìn gbé lọ
- Kí ló fa ìjà láàárín Eedris Abdulkareem àti Festus Keyamo?
- Ẹgbẹ́ Oduduwa Republic Agitators ní ìwọ́de alágbára ń bọ̀ l‘Osun
Ọ̀rọ̀ gómìnà yìí wáyé nítorí ọ̀pọ̀ ló n ké gbàjarè pé, wọ́n kò gbọ́ òhunkóhun láti ẹnu gómìnà láti ìgbà tí ọ̀rọ̀ ìpàniyàn àwọn Boko Haram ti bẹ́ sílẹ̀, tí ọ̀pọ̀ sì ti sá kúrò ní ibùgbé wọn.
Awọn eeyan miran ló ni àwọn ti sá kúrò ni ibùgbé àwọn nítorí wọn kò fẹ́ kí ọwọ́ja igbésùmọ̀mí náà kan awọn, nígbà ti Boko Haram àti àwọn ọmọ ogun bá nkojú ara wọn.

Oríṣun àwòrán, HQNigeriaArmy
Ẹ̀wẹ̀, Gómìnà Buni sọ fún BBC pé, kìí ṣe pé òun jòkó káwọ́ gbera, sùgbọ́n òun ń bá àwọn ọmọọgun sọ̀rọ̀ ní Abuja láti ìgbà dé ìgbà, lójúnà à ti rí ojúùtú sí ìsòrò tó wà nílẹ̀.
Gómìnà ní sáájú àsìkò yìí, àwọn agbésùmọ̀mí yìí máa n wá láti jí oúnjẹ àti nǹkan ìní àwọn ènìyàn sùgbọ́n lásìkò yìí, wọ́n jòkó pa sínú ìlú ni, fún ọ̀pọ̀ ọjọ́.
Inú hilàhílò ni ọ̀pọ̀ ará ìlú wà, tí ọ̀pọ̀ sí fi ìlú sílẹ̀ láti farapamọ́ láwọn ìlú tó wà ni tòsí wọn.
"Mó sì n bá ọga agba awọn ológun l'Abuja sọ̀rọ̀ láti wá ọ̀nà abáyọ sí ọ̀rọ̀ yìí àti lati mú kí nǹkan bọ́ sípò ní ìpińlẹ̀ wa," Mai Mala Buni sọ èyí.
"Sùgbọ́n gómìnà fi ẹ̀dùn ọkàn rẹ̀ hàn pé ní ìpínlẹ̀ naa, àwọn yóò ṣapa láti mú nǹkan padà bọ̀ sípò, kí Abuja to gbe ìgbésẹ̀.
Kíló ǹ ṣẹlẹ̀ gan
Láti bi ọjọ́ díẹ̀ sẹ́yìn ni ìkọ alákatakítí Boko Haram ti tún tẹra mọ́ ìkọlu Geidam àti àwọn ìpińlẹ̀ mííràn, ni àgbégbé ilà-òòrùn àríwá Nàìjíríà.
Láàrín àwọn ti wọ́n pa nínú ìṣẹ̀lẹ̀ ọjọ́ Eti ni obìnrin kan ti rọ́kẹ́ẹ̀tì tí wọn jù mọ́ ilé ìyá ọkọ́ rẹ̀ ti báa, lásìkò tó ṣàbẹ̀wò sí Geidam.
Ìròyìn sọ pé, àwọn agbésùnmọ̀mí tún já ilé àti sọ́ọ̀bù, tí wọn sí kó ọ̀pọ̀ ounjẹ lọ.
Ìjà tún bẹ́ sílẹ̀ láàrín àwọn agbésùnmọ̀mí àti àwọn ọmọogun Nàìjíríà, ní ìlú Mainok ni ìpínlẹ̀ Borno, tí ìròyìn sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé ọ̀rọ̀ náà kan àwọn ọmọogun.
A gbọ́ pé àwọn ọmọogun dá ààrin àwọn ikọ agbésùmọ̀mí rú nígbà tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ní yìbọ́n ni Mainok.
Ìròyìn mííràn tún sọ pé, wọ́n jí irínṣẹ́ àwọn ọmọogun lọ, tí wọ́n sì pá àwọn mííràn.
Ẹ̀wẹ̀, gbogbo ìgbìyànjú láti bá agbẹnusọ ologun Brigadier General Muhammad Yerima sọ̀rọ̀ ló já sí pàbó.
Ètò ààbò ń búru sí lójoojúmọ ni lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, èyí sì tí mú kí àwọn òǹwòye sọ pé ẹ̀rù ń ba àwọn fún ọjọ́ iwájú Nàìjíríà.
Eyi ri bẹẹ ni pàápàá jùlọ nítorí ìròyìn tó sọ pé ǹkan ìjà ogun kò tó mọ́ fún àwọn ọmọogun Nàìjíríà lati fi sisẹ.

Boko Haram sígun bo ìpínlẹ̀ Yobe, ikọ̀ ọmọogun òfurufú dojú ìbọn kọ wọ́n

Oríṣun àwòrán, NAF
Saaju la ti mu iroyin wa fun yin pe ikọ ọmọogun Naijiria ni awọn ti bori ikọ agbesunmọmi Boko Haram to ṣigun bo agbegbe Geidem nipinlẹ Yobe.
Ikọ ọmọogun ni awọn ọmọogun ofurufu to gbe ọkọ ofurufu lo bori wọn ninu atẹjade ti wọn fi lede.
Iroyin ni ikọ ọmọogun Boko Haram wọ ọkọ ologun wo agbegbe naa ni iha ila oorun ariwa orilẹede Naijiria.
- Adunni Olorisa, obìnrin òyìnbó tó di ìyàwó òrìṣà nílẹ̀ Yorùbá títí di ọjọ́ ogbó
- Ẹjọ́ ń bẹ lọ́run fún gbogbo ẹ̀yin tí kò wàásù fáwọn tó ń tẹ lé yín lórí Instagram àti Facebook- Mike Bamiloye
- Àwọn Olùkọ́ Yorùbá ní ìpínlẹ̀ Osun ṣe bẹbẹ lórí ètò Akomọlede àti Aṣa lórí BBC
- Àtẹ̀jádé ìjọba apapọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Pantami fihàn pé wọ́n ń káànú ìgbésùnmọ̀nmí- PDP
- Mo fẹ́ ìyàwó méjì lọ́jọ́ kan ṣoṣo láti ṣe ju ohun tí bàbá mi gbé ṣe - Uloho Othuko
Boko Haram ṣekọlu naa si awọn eniyan ti wọn n jẹun lati ṣinu awẹ Ramadan ti wọn n gba lọwọ.

Oríṣun àwòrán, NAF
Awọn ti iroyin naa ṣe oju wọn ni o le ni ogun awọn ikọ Boko Haram ti wọn ṣekọlu si agbegbe Geidam ọhun, ko to di wi pe ọkọ ija ti ofurufu de lati koju wọn.
Agbegbe Geidem ni ipinlẹ Yobe ọhun ni Adele Ọga Ọlọpaa lorilẹede Naijiria, Usman Alkali Baba ti wa.

Ikọ ọmọogun ni awọn koju lara awọn ikọ Boko Haram nibi ti wọn ti n salọ lẹyin ti wọn jawọ atako naa.
Amọ ko tii si ẹni to le e sọ iye eniyan ti ẹmi wọn ti ba iṣẹlẹ naa lọ.
- Ṣé irúfẹ́ oúnjẹ tí ò ń jẹ́ lè jẹ́ kí o gbádùn ìbálòpọ̀ rẹ síi?
- Ṣé irúfẹ́ oúnjẹ tí ò ń jẹ́ lè jẹ́ kí o gbádùn ìbálòpọ̀ rẹ síi?
- Àwọn agbébọn ti pa mẹ́ta nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ fásitì Greenfield tí wọ́n jí gbé ní Kaduna
- Olólùfẹ́ Naira Marley kọ sẹ́nu tírélà nítorí ₦500 tó fẹ́ gbà lọ́wọ́ rẹ̀
- Àwọn alákòso BCOS tan ìmọ́lẹ̀ sí ọ̀rọ̀ iléègbé àwọn òṣíṣẹ́ tí ìjọba ìpínlẹ̀ Oyo bẹ̀rẹ̀ sí ń wó
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Yobe, ASP Dungus Abdulkarim ni ikọ Boko Haram naa ti wa saaju lati wa pin iwe fun awọn eniyan lati ma a reti awọn, nitori awọn nbọ lati wa sọ ipinlẹ Yobe da ipinlẹ awọn musulumi (Islamic State).


















