Ilé ìgbìmò aṣofin Niger bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ láti fòfin dé ìbálòpọ̀ láàárín akọ sí akọ.

Aworan

Oríṣun àwòrán, AFP

Ẹgbẹ kan ninu awọn aṣofin ni orilẹede Niger ti ṣe atilẹyin fun abadofin ti o n pe fun ifiyajẹ ibalopọ laarin akọ si akọ ati abo si abo. Pupọ ninu awọn eeyan ni orilẹ ede Niger lo jẹ Musulumi, amọ ti ko sí ofin kankan ti o dena ibalopọ laarin ẹniyan ara kan naa bayii. Awọn ọmọ ile-igbimọ aṣofin ni orilẹede naa sọ pe ibalopọ-laarin eya ara kan naa lodi si ẹsin ati aṣa orilẹ-ede naa.

Abadofin naa ni Nana Djibou Harouna gbe kalẹ niwaju alakoso Ile-igbimọ aṣofin nibi ijokoo ile naa to waye ninu ọsẹ.

Iyaafin Harouna ṣapejuwe ibalopọ laarin akọ si akọ ati abo si abo gẹgẹ bi “iṣoro ti o kan gbogbo awujọ ni orilẹ-ede naa."

O sọ pe awọn ti ṣe ifọrọwanilẹnuwo fun awọn ọmọ orilẹ-ede naa lati mọ iha ti wọn kọ ki awọn to gbe aba ọhun siwaju ile.

O fi kun pe awọn ti gba atilẹyin awọn ara ilu, ti awọn ọmọ ile igbimọ aṣofin orilẹ-ede naa si fọwọsi.

Ko i tii si gbedeke igba tawọn aṣofin naa maa fi jiroro lori abadofin ọhun ati iru ijiya ti wọn fẹ fi sinu ofin naa.

Igbesẹ yii lo n waye lẹyin ti ile-ẹjọ kan ni Maradi da awọn ọdọbinrin meji lare fun awọn ẹsun to jọmọ ibalopọ laarin obinrin si obinrin nitori ko si ofin ti o han gbangba to gbogun ti ibalopọ laarin eya ara kan naa.