Mo mọ̀ pé èmi ni mo ni gbogbo àwọn èèyàn Ogun, báa bá fẹ́ dìbò àmọ́ mi ò lè kó wọn silẹ̀ fún ẹnikẹ́ni - Sẹ́nétọ̀ Yayi
Saa meji ni Sẹnetọ Solomon Olalekan ti lo nile igbimọ aṣofin Naijiria nibi to ti ṣoju ẹkun Iwọ-Oorun ipinlẹ Eko.
Ni bayii, o n gbero lati ṣe saa kẹta nile aṣofin aṣofin bayii gẹgẹ bi aṣoju ẹkun Iwọ- Oorun nipinlẹ Ogun.
Bakan naa, o mẹnu ba aawọ to suyọ laarin rẹ, gomina ana nipinlẹ Ogun Ibikunle Amosun ati gomina to wa lori alefa lọwọlọwọ nipinlẹ Ogun, Dapo Abiodun.

Gẹgẹ bi ọpọlọpọ ṣe maa n pe e, Yayi ninu ifọrọwanilẹnuwo pẹlu BBC Yoruba ṣalaye idi ati bo ṣe rii ṣe to re lati ipinlẹ Eko si Ogun to si tun fẹ jẹ Sẹnetọ.
Bakan naa, o sọ idi ti ipo Sẹnetọ Ogun West ṣe tọ sii ju gbogbo awọn to ku ti wọn jọ n du ipo naa to sijẹ pe inu oṣelu Ogun ni wọn bi awọn si.
Yayi tun fesi lori ọrọ ti awọn eeyan maa n sọ pe owo gọbọi gọbọi lawọn aṣofin n gba, o ni irọ gbaa ni.












