Tinubu: Ọjà tí kò le kùtà ni mí tẹ bá tì mí lẹ́yìn láti di ààrẹ

Oríṣun àwòrán, officialbolatinubu/Instagram
Eekan ẹgbẹ oṣelu APC lorilẹede Naijiria, Aṣiwaju Ahmed Tinubu, to n dije fun ipo aarẹ labẹ aṣia ẹgbẹ APC ti sọ pe laifọtape, ninu gbogbo awọn eeyan to n dije fun ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023 bayii, oun nikan lo duro deede.
Tinubu, to ba awọn ọmọ ẹgbẹ oṣelu APC to wa nile aṣofin-ṣoju sọrọ ṣalaye pe eeyan o jayopa bi wọn ba sọ pe oun loun pegede figbọrọ jẹka julọ laarin wọn.
Bakan naa ni Tinubu tun lo anfaani ipade to se pẹlu awọn asofin naa lati sọrọ lori iwe ẹri to ni ni fasiti.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wọ́n fi abẹ dá ọgbẹ́ sí Timothy Adegoke lára ni, kí ẹ̀mí tó bọ́ lára rẹ̀ - Onímọ̀ ìwádìí
- Ọ̀kan lára àwọn afurasí mẹ́rin tó gé orí Sofiat Okeowo láti fi ṣẹ́ṣó gba ìtúsílẹ̀
- Kìnìún yawọ ìlú, ṣe ọlọ́dẹ méjì léṣe
- 1200 èèyàn rì sábẹ́ ilẹ̀ bí Russia ṣe yin àdó ikú mọ́ gbọ̀ngàn nlá kan ní Ukraine
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ní àwọn awakọ̀ èrò fẹ́ ṣe ìwọ́de lónìí l‘Eko torí yíyọ MC Oluomo nípò?
- Kí ló fa rògbòdìyàn tó gbòde ní Ajah, tí ẹ̀mí méjì fi bọ́, tí ọ̀pọ̀ dúkìá sì bájẹ́?
- "Sylvester Oromoni tọ̀ mí wá pé itan ń ro òun kó tó kú, mo sì ba fi ọwọ́ ra á pẹ̀lú òògùn ara ríro"
- Ìwà àtakò sí ìjọba ní bí ọlọ́pàá bá da iṣẹ́ sílẹ̀, kò tọ̀nà - Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá
- Kò pọn dandan fún akẹ́kọ̀ọ́bìnrin láti lo hijab nílé ẹ̀kọ́ - Ilé ẹjọ́
Ọpọ awuyewuye lo si ti figbakan ri waye lori boya iwe ẹri asaaju ẹgbẹ oselu APC naa jẹ ojulowo tabi ayederu.
First class ni mo mu jade nile ẹkọ fasiti:
Tinubu sọ fun awọn aṣofin apapọ naa pe iwe ẹri onipo kini ni fasiti, iyẹn 'first class' loun ni jade nileewe giga fasiti.
Bakan naa lo tun yan leti awọn aṣofin to jẹ ọmọ ẹgbẹ APC naa pe, alaimọ ohun to tọ ni gbogbo awọn to n ba oun du ipo aarẹ fọdun 2023.
" Yatọ si ibeere ati idahun, pupọ awọn to n ba mi dije yii ko ni anfani kankan lati ṣe fun orilẹede Naijiria.
"Emi o wa lati wa yin ara mi o. Mo kan wa lati wa sọ fun yin ni pe mo jẹ ọja ti ko lee kuta fun un yin lati ta.
Emi nikan, ninu awọn oludije wọnyii ni mo jafafa julọ fun ipo aarẹ Naijiria lọdun 2023"

Oríṣun àwòrán, officialbolatinubu/Instagram
Àwọn tó ń bá mi du ipò ààrẹ ni kò mọ ohun tó kàn fún Nàìjíríà
Ki lesi tawọn aṣofinṣoju fun Tinubu?
Olori awọn ọmọ ileegbimọ aṣofinṣoju to pọ julọ, Honorebu Ado Doguwa fi da Aṣiwaju Tinubu loju pe gbogbo awọn lawọn yoo ṣiṣẹ fun un.
Bi ẹ ko ba ni gbagbe, Họnọrebu Doguwa yii kan naa lo ko awọn aṣofin kan lati apa ariwa orilẹede Naijiria sodi wa Tinubu lọ sorilẹede Gẹẹsi, nigba ti ara rẹ ko ya.

Ọ̀nà ti di fáwọn tó kúndùn láti máa yí èsì ìdìbò - Makinde

Oríṣun àwòrán, Others
Gómìnà ìpínlẹ̀ Oyo, Seyi Makinde ní ohun gbogbo ti padà bọ̀ sípò lórí jíjẹ oyè Olubadan sí bí ó ṣe wà ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀.
Makinde sọ èyí níbi ètò ilé ìjọsìn St. Peters Anglican Church, Aremo, Ibadan láti ṣàmì ayẹyẹ ọ̀sẹ̀ àṣà Ibadan tí ọdún 2022 tó bẹ̀rẹ̀ lọ́jọ́ Àìkú, ọjọ́ kẹtàlá ọdún 2022.
Gómìnà wòye pé bí àwọn kò bá tètè parí aáwọ̀ tó súyọ lórí jíjẹ oyè Olubadan ní kíákíá ó ṣeéṣe kí aáwọ̀ bẹ́ẹ̀ máa súyọ ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá fẹ́ jẹ oyè Olubadan.
Àtẹ̀jáde kan látọwọ́ agbẹnusọ gómìnà Makinde, Taiwo Adisa ní lóòótọ́ ni ó gba àwọn ní àkókò díẹ̀ láti yan Olubadan tuntun bí ó yilẹ̀ jẹ́ pé kò yẹ kó gba àwọn ní ọ̀sẹ̀ kan sí méjì lọ.
Ṣùgbọ́n ó ní bí àwọn kò bá paná aáwọ̀ náà kí àwọn tó gbé adé le Olubadan tuntun lórí, Ibadan yóò máa kojú ìpèníjà bẹ́ẹ̀ lọ́jọ́ ìwájú lásìkò tí wọ́n bá jẹ oyè.
Bákan náà ló fi kun pé àtìlẹyìn àwọn ara Ibadan ló ṣokùnfà ní ìpẹ̀tù sí aáwọ̀ ṣe lọ ní ìrọ̀wọ́ rọsẹ̀.
Bẹ́ẹ̀ náà ló tẹ̀síwájú pé òun ti ṣe ìlérí fún àwọn ìgbìmọ̀ tó ń ṣètò ayẹyẹ ọ̀sẹ̀ Ibadan láti má mikàn pé ayẹyẹ náà yóò wáyé pẹ̀lú Olubadan lórí ìtẹ́.
- Wo àwọn òṣèré tíátà tó ti fún Kemi Afolabi lẹ́bùn àtàwọn tó ń kíi lẹ́yìn tó kéde àìsàn rẹ̀
- Ìyáwó Abba Kyari dákú nílé ẹjọ́ bí adájọ́ ṣe kọ̀ láti gba béèlì ọkọ rẹ̀
- Olóyún kan àti ọmọ inú rẹ kú nígbà ti Russia sọ àdó ikú sílé ìwòsàn ní Ukraine
- Ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ! Ìyá ọmọ́ yọjú pé ‘Dispatch Rider’ tí wọn ká ọmọ mọ́ lọ́wọ́, kìí ṣe gbọ́mọ-gbọ́mọ
- Ìbẹ̀rù kòbókò ló mú mi sá nílé kéú, mo bẹ̀rù ẹgba - Obasanjo
- Ọ̀rọ̀ yóò lẹ́yìn bí China bá ṣerànwọ́ fún Russia lórí ogun Ukraine - Amẹ́ríkà lọgun
- ASUU fi ọ̀sẹ̀ mẹ́jọ kún ìyanṣẹ́lódì tó n lọ lọ́wọ́, ètò ẹ̀kọ́ ní fásitì di kọ̀
- Àlùfáà ìjọ gbé egbògi olóró “cocaine”, ó kó sí gbaga NDLEA
- Wo ọmọ Yorùbá mẹ́ta àti gbajúmọ̀ míì tó ní Lupus, àrùn tó n bá Kemi Afolabi fínra
Makinde rọ àwọn ènìyàn láti máa kópa nínú ètò idibò, bí ọ̀nà ṣe pin fún àwọn tó máa ń yí èsì ìdìbò
Gómínà Makinde tún pàrọwà sí àwọn ènìyàn láti máa kópa níbi ètò òṣèlú, kí wọ́n sì máa dìbò lójúnà àti lè máa yan ẹni tó wù wọ́n sípò olórí, kí wọ́n le lẹ́nu ọ̀rọ̀ tí àwọn olórí kò bá ṣe dáadáa tó.
Ó ní pẹ̀lú òfin tuntun tó wà lórí ètò ìdìbò báyìí, kò sí àyè fún ṣíṣe èèrú èsì ìdìbò, gbogbo ènìyàn ló ní àǹfàní láti mọ bí ó ṣe ń lọ nínú òṣèlú àti pé àìsí níbẹ̀ ni àìbá wọn dási.
Bákan náà ló ní ìgbà tí àwọn kan máa ń kọ èsì ìdìbò tó bá wù wọ́n lórí níbi àkọ́jọ ètò ìdìbò ti di àfìsẹ́yìn tí eégún fi aṣọ.
Bẹ́ẹ̀ ló fi kun pé ayé tí àwọn kan yóò jòkòó sí ibì kan máa kọ èsì ti kọjá, kí oníkálùkù wà ní ojú lalákàn fi ń ṣọ́rí ni báyìí.
Àwọn ará Ibadan gbóríyìn fún gómìnà Makinde lórí oyè Olubadan
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀, Ààrẹ ọmọ bíbí ìlú Ibadan, Ọmọọba Oluyemisi Adeaga dúpẹ́ lọ́wọ́ gómìnà Seyi Makinde fún bó ṣe parí aáwọ̀ lóí oyè Olubadan ní tùbí ń nùbí.
Adeaga ní ṣíṣe ètò ìjọsìn náà wáyé láti dúpẹ́ fún Ọlọ́run lórí bí ètò gbígbé ọ̀pá àṣẹ lé Olubadan lọ́wọ́ láìsí ìdíwọ́ kankan.


















