Malami: Ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ Oduduwa ní Mínísítà fétò ìdájọ́ ń tẹ̀lé òfin lábẹ́ ìjọba alágbádá

Oríṣun àwòrán, Blueprint
Ẹgbẹ awọn ọdọ ọmọ Oduduwa lagbaye ti fi oye Omoluabi da Agbẹ́jọ̀ro agba ati Minisita feto idajọ, Abubakar Malami lọla lori bo se sisẹ sin ilẹ baba rẹ pẹlu ootọ.
Amugbalẹgbẹ feto iroyin fun minisita naa, Umar Jubrilu Gwandu lo kede bẹẹ ninu atẹjade kan to fisita.
Akinyele Olasunbo, tii se agbẹnusọ fun ẹgbẹ ọdọ Oduduwa lagbaye, wa se apejuwe Malami bii ọmọ Naijiria ti ko mọ ti ara rẹ nikan amọ n ri daju pe isejọba awa ara awa to ba ofin mu fẹsẹmulẹ pẹlu idajọ ododo lai segbe.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Dandan kọ́ ni kí o ṣe àyẹ̀wò DNA tí kò bá sí ẹni tó n bá ọ du ọmọ rẹ - Rotimi Salami
- Ìdúnkokoòmọ́ni nípa ẹ̀yà ni iwọ́de Yoruba Nation, IPOB tó wáyé l‘Amẹ́ríkà - Garba Shehu
- 'Àwa Ọlọ́pàá ò lè sọ bóyá lóòtọ́ ọmọ Yahoo ló ju òkú obìnrin s'ẹ́gbẹ̀ẹ́ ṣọ́ọ̀ṣì, ẹní bá mọ̀ọ́ kó fojú hàn'
- Ọlọ́pàá, Amotekun àti figilanté kán lu igbó láti wá àwọn tó pa ọlọ́pàá méjì ní báńkì Iragbiji, Osun
- 'Àyẹ̀wò ìdákọ́ńkọ́ mi gẹ́gẹ́ bí akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ nípa ìhùwàsí ọmọde fihàn pé Baba Ijesha fọwọ́ kan ọmọ Princess lọ́nà tí kò tọ́'
- Ìpanu ''small chops'' ló mú kí sọ́jà da omi ìdọ̀tí lé mi lórí - Corper Fidelia
O fikun pe ipa ti minisita feto idajọ naa ko lati gbogun ti iwa ijẹkujẹ lo ti n so eso rere, to si tun ti mu agbega ba igbe aye ati ayanmọ ọmọ Naijiria.
Olasunmbọ wa kan saara si Malami lori bo se n saaju awọn ọlọpọlọ pipe ọmọ Naijiria ni ẹka eto idajọ, eyi to ni o mu ki o tayọ ni gbogbo ọna, to si jẹ awokọse rere.
Nigba to n fesi, Abubakar Malami, ẹni ti amugbalẹgbẹ aarẹ Buhari nidi igbogun ti iwa ọdaran nidi owona, Amofin Abiodun Aikomo soju fun wa fi ẹmi imoore han si ẹgbẹ ọdọ Oduduwa naa.
O wa mẹnuba ojuse pataki ẹgbẹ ajafẹtọẹni nidi aseyọri awọn eto idagbasoke eyi ti yoo ri daju pe agbega bawọn agbegbe igberiko wa.









