Pierre Buyoya: Coronavirus ni wọn ló pa ààrẹ tẹ́lẹ̀ náà lẹ́ni ọdún 71

Oríṣun àwòrán, AFP
Aarẹ tẹlẹ ni orilẹede Burundi, Pierre Buyoya ti jade laye lẹni ọdun mọkanlelaadọrin.
Mọlẹbi oloogbe naa to fidi isẹlẹ naa mulẹ fun BBC ni Buyoya dagbere faye nilu Paris ni Ọjọbọ lati ipasẹ arun Coronavirus.
Ọgagun to ti fẹyinti naa lo lo ọdun mẹtala lori aleefa lẹyin to fi ipa gba ijọba lọwọ awọn asaaju rẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọla Adedibu ní Ladoja jẹ̀ tó fi wọlé Gómìnà l‘Oyo labẹ ẹgbẹ́ PDP - Obasanjo
- Sé Boko Haram ń pẹ̀ka kiri Nàíjíríà ní ìjínigbé ṣe burú báyìí?
- Ẹ̀sìn kò fàjà! Obìnrin Mùsùlùmí ṣe ilé àlúfà ní ọ̀ṣọ́ fún Kérésìmesì
- Àwọn gómìnà nílẹ̀ Yorùbá ti kùnà láti pèsè ààbò tó péye fún aráàlú - Ẹgbẹ́ Majeobaje
- Ọ̀fẹ́ ló bá dé, Boko Haram kọ́ ló jí akẹ́kọ̀ọ́ gbé, a kò san kọ́bọ̀ fún ìdáǹdè wọn - Masari
- Ṣé lóòtọ́ ni Bimpe Oyebade lóyún fún Lateef Oladimeji?
- Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ nìkan ni ọ̀nà abáyọ sí ìṣòro Nàìjíríà- Olusegun Obasanjo
- Ìtura ìgbà díẹ̀ ni bọ́dà tí ìjọba ṣí padà, kò lóòre nínú - Onímọ̀ ọrọ̀ ajé
- Wo ìdí tí ààrẹ Buhari kìí fi ṣe ẹ̀dà Jubril láti Sudan
Ni osu Kẹwa ọdun 2020 ni ile ẹjọ kan nilẹ Burundi ran lẹwọn lai si nibẹ lori ẹsun pe o gba ẹmi aarẹ akọkọ ti araalu dibo yan lorilẹede naa, Aarẹ Melchior Ndadaye lọdun 1993.
Isẹlẹ naa si ni wọn lo sokunfa rogbodiyan to ran eeyan bii ẹgbẹrun lọna ọọdunrun lọ sọrun.

Oríṣun àwòrán, Twitter@Pierre Buyoya
Amọ Buyoya ni oun ko jẹbi ẹsun asemase kankan rara.
Ni osu to kọja ni Buyoya kọwe fipo silẹ gẹgẹ bi asoju ajọ isọkan orilẹede Afirika si ilẹ Sahel pẹlu awijare pe oun fẹ gbajumọ ọna lati wẹ orukọ oun mọ.








