Adeleke: Iléẹjọ́ dá Sẹ́nétọ̀ Adeleke sílẹ̀ lórí ẹ̀sùn màgòmágó ìdánwò tí wọn fi kàn án

Oríṣun àwòrán, Facebook/SEN Ademola Adeleke
Ile ẹjọ giga ijọba apapọ niluu Abuja ti dajọ pe oludije gomina fẹgbẹ oṣelu PDP nipinlẹ Oṣun, Ademola Adeleke ko jẹbi ẹsun magomago lasiko idanwo ti wọn kan an.
Adajọ Inyang Ekwo to dajọ ọhun lọjọ Ẹti lo paṣẹ wi pe ki Sẹnetọ Adeleke maa lọ lalaafia.
Simon Lough tii ṣe agbẹjọro awọn olupẹjọ sọ fun adajọ Ekwo l'Ọjọbọ pe awọn olupẹjọ fẹ ki ẹjọ naa wa sopin nitori bi Adeleke ko ṣe maa yọju nigba kugba ti igbẹjọ ba n lọ lọwọ.
- Kàyééfì BBC News Yorùbá gbé òtítọ́ òògun owó yẹ̀wò
- Ọmọ pupa làwọn olólùfẹ́ wa fẹ́ wò nínú fíìmù làwọn òṣèré tíátà fi ń bóra - Muka Ray
- Mo wọ bàtà àti fìlà wọ pẹpẹ Cele láti ṣe wáàsí, kò sí ṣọ́ọ̀ṣì tí n kò le wọ̀ - Sheik Buhari ọmọ Musa
- Gómìnà Ondo Akeredolu ṣí ilẹ̀kùn ṣọ́ọ̀ṣì àti mọ́ṣáláṣí sílẹ̀ fún ìjọ́sìn
- Ìtàn ìgbésí ayé Oshodi, ọmọ Tápà léǹpe tó di akọni ní ìlú Eko
- Femi Adebayo di àgbà àáfà òníláwàní, Iyabo Ojo fi sìgá dárà, Allwell Ademola di ọmọdé padà, tí Wazo si bímọ tuntun
Adeleke ko tii yọju sile ẹjọ lati ọjọ kẹfa oṣu karun un ti ileẹjọ ti fun un laye lati rinrin ajo lọ si orilẹede Amẹrika fun itọju ara rẹ.
Ọga ileewe girama Ojo-Aro ti Adeleke ti ṣedanwo, Sikiru Adeleke, Alhaji Aregbesola Muftau to jẹ akọwe ileewe naa ati olukọ kan nibẹ Dare Samuel Olutope, gbogbo wọn lọ nileẹjọ pe awọn o jẹbi ẹsun ti wọn fi kan awọn.
Agbẹjọro Adeleke. Alex Izinyon (SAN), naa ko tako aba lati wọgile ẹjọ ti wọn pe onibara rẹ.
Ohun ti agbẹjọro agba naa sọ fun adajọ ni pe ko paṣẹ idasilẹ oludije ibo gomina Oṣun, Ademola Adeleke.








