N37b for NASS: 'Ilé aṣòfin àgbà l'Abuja le dà wó lulẹ̀ láì ṣe àtúnṣe rẹ̀ ní kíákíá'

Ile aṣofin l'Abuja

Oríṣun àwòrán, Twitter/Nigerian The Senate

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 3

Awuyewuye lori igbeṣẹ ijọba lati lo biliọnu mẹtadinlogoji lati fi se atunse Ile Igbimọ Asofin apapọ ni ilu Abuja ko tii tan nilẹ.

Lẹyin tawọn ajọ SERAP atawọn ajọ ajafẹtọ miiran ti tako igbesẹ ijọba naa, awọn aṣoju-ṣofin kan naa ni owo ọhun pọ ju fun atunṣe gbọngan ile aṣofin.

Koda wọn ni o san ki ijọba apapọ lo owo naa fun ipese ohun amayedẹrun fawọn ọmọ Naijria.

Amọ agbẹnusọ fun ile igbimọ aṣofin agba l'Abuja, sẹnẹtọ Godiya Akwashiki ti tutọ soke foju gba a lori ọrọ naa lẹyin to sọ wi pe, kii kuku ṣe pe ile aṣofin ni yoo gbowo naa ṣọwọ.

O ni ajọ to n mojuto olu-ilu orilẹede Naijiria, FCDA ni yoo ṣagbatẹru iṣẹ atunṣe ile naa.

Sẹnẹtọ Akwashiki ojuṣe ile aṣofin ni lati fi to ijọba leti ipo ti ile aṣofin wa, eleyi to ni o le da wo bi iṣẹ atunṣe ko ba waye lori rẹ ni kiakia.

Aṣofin Akwashiki fikun ọrọ rẹ pe ajọ FCDA lo mọ ohun to ri ko to sọ pe biliọnu mẹtadinlogoji lohun ma nilo lati ṣatunṣe ile.

O ni to ba wu Aarẹ Muhammadu Buhari, o le ranṣẹ pe awọn kọngila ti FCDA fẹ gbe iṣẹ naa fun lati wa ṣalaye bi wọn ti fẹ nanwo naa.

Àwọn aṣòfin mẹ́ta takò lílo N37b f'àtúnṣe Ilé Aṣòfin Àpapọ Nàìjíríà

Asojusofin mẹta lo ti bu ẹnu atẹ lu igbeṣẹ ijọba lati lo biliọnu mẹtadinlogoji lati fi se atunse Ile Igbimọ Asofin apapọ ni ilu Abuja .

Asojusofin mẹta lo ti bu ẹnu atẹ lu igbeṣẹ ijọba lati lo biliọnu mẹtadinlogoji lati fi se atunse Ile Igbimọ Asofin apapọ ni ilu Abuja .

Akin Alabi ati Ochilegor Idagbo

Oríṣun àwòrán, @others

Àkọlé àwòrán, Wọn ni iba dara ki ijọba fi owo naa ran awọn olokowo kekeke lọwọ

Eyi ko ṣẹyin bi Ile Igbimọ Asofin se gbe jade ninu eto isuna fun ọdun 2020 wi pe wọn yoo nilo owo yii lati tọ̀'ju Ile Igbimọ Asofin.

Ni oju opo Twitter ni Asojusofin Oloye Akin Alabi, Ochilegor Idagbo ati Bamidele Salam ti sọrọ tako igbeṣẹ wọn yii.

Wọn fikun wi pe ki wọn lo owo naa lati fi pese ile iwosan fun awọn eniyan, idokowo kekeeke ati ohun amayedẹrun miran fun awọn ọmọ Naijiria.

Oloye Akin Alabi sọ pe o dara ki ijọba apappọ na owo naa lati fi ṣe atunsẹ awọn ile iwosan ati ile wa ju ki wọn na owo naa fun atunsẹ Ile Igbimọ Asofin apapọ.

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Bamidele Salami naa ko gbẹyin ni bi o ṣe bu ẹnu atẹ lu eto iṣuna ọhun.

O sọ pe "Gẹgẹ bi ọmọ ile Igbimọ Asojusofin, mi o lero pe a nilo biliọnu mẹtadinlogoji fun atunṣe ile naa bayii."

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Salam ṣalaye pe kaka ki ijọba na owo yii si Ile Igbimọ Asofin apapọ, iba dara ko fi owo naa ran awọn olokowo kekeke lọwọ.

O ni oun yoo gbe igebsẹ lati tako abadofin naa ni igab ti ile ọhun ba bẹrẹ iṣẹ loṣu kinni ọdun 2020.

Àkọlé fídíò, 'Àṣà wa l'Ekiti ló dára jú lórílẹ̀èdè Nàìjíríà'

Eyi ko ṣẹyin bi Ile Igbimọ Asofin se gbe jade ninu eto isuna fun ọdun 2020 wi pe wọn yoo nilo owo yii lati tọ̀'ju Ile Igbimọ Asofin.

Ni oju opo Twitter ni Asojusofin Oloye Akin Alabi, Ochilegor Idagbo ati Bamidele Salam ti sọrọ tako igbeṣẹ wọn yii.