Yollywood. Olanrewaju James Omiyinka: Ajẹ́rìí Bàbá Ijesha sọ fún ilé ẹjọ́ pé òun ò gbà pé fọ́nrán tí wọ́n fi léde kìí ṣe èyí tí wọ́n ti tọwọ́ bọ̀.

Ajẹ́rìí Bàbá Ijesha sọ fún ilé ẹjọ́ pé òun ò gbà pé fọ́nrán tí wọ́n fi léde kìí ṣe èyí tí wọ́n ti tọwọ́ bọ̀.
Gbajúgbajà òṣèré tíátà, James Olanrewaju tí gbogbo ènìyàn sí Bàbá Ijesha ti ní òun kò gba pé àkóónú tó wà nínú fọ́nrán CCTV tí wọ́n gbé wá sílé ẹjọ́ tako òun jẹ́ òótọ́.Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀
Elẹ́rii Bàbá Ijesha tó jẹ́ onímọ̀ nípa ṣíṣe àtúnṣe àti fífi ẹ̀rọ CCTV sílé, Adeleke Lawrence sọ èyí nílé ẹjọ́ lánàá nígbà tó ń fèsì sí ìbéèrè tí agbẹjọ́rò Bàbá Ijesha, Babatunde Ogala (SAN) bèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
Ẹ̀sùn bíbá ọmọdé ní ìbálòpọ̀ àti ẹ̀sùn márùn-ún mìíràn tó jọ mọ́ bíbá ọmọdé lájọṣèpọ̀ ni Bàbá Ijesha ń kojú ní ilé ẹjọ́ tó ń gbọ́ ẹ̀sùn ìfìyàjẹni àti ìbálòpọ̀ tó wà ní Ikeja, ìpínlẹ̀ Eko.
- Ìwádìí tó kúná ni a fẹ́ láti mọ̀ àwọn Onígbọ̀wọ́ olóògùn owó ní Oja Odan- Oba Oladiipo Oyebamiji
- Amotekun Ondo gbẹ́sẹ̀lé ọkọ̀ àjàgbé tó ń kó àwọn ọ̀dọ́ 63 láti Gombe lọ sí Eko
- Ẹ̀kún omi gbé èèyàn méjìdínlógójì lọ nílùú Petrópolis ní orílẹ́èdè Brazil
- EFCC gbẹ́sẹ̀lé dúkìá ọ̀gá olọgun tí iye rẹ̀ tó ₦10.9b
- Iléẹjọ́ tún sún ìgbẹ́jọ́ olórí ẹgbẹ́ IPOB Nnamdi Kanu síwájú
- Wo ọkùnrin kan tó fi N1.2m gbẹ́ ibojì rẹ̀ sílẹ̀ nígbà tó sì wà láàyè
- Kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn rẹ láti yé da àlááfíà ìlú láàmú- Ìjọba ìpínlẹ̀ Osun sí Aregbesola
Kíló ṣẹlẹ̀ nílé ẹjọ́ lánàá?
Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀.
Fọ́nrán mẹ́rin tó ṣàfihàn ohun tó ṣẹlẹ̀ lórí ẹ̀sùn bíbá ọmọdé lòpọ̀ tí wọ́n fi kan Bàbá Ijesha ni Ogala bèrè fún láti wò.
Nínú oṣù kẹrin, ọdún 2021 ni gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú Princess fẹ̀sùn kan Baba Ijesha pé ó bá ọmọ ọdún mẹ́rìnlá tó ń gbé lọ́dọ̀ òun sùn, tó sì fi àwọn fọ́nrán mẹ́rẹ́ẹ̀rin náà lédé gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí.
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí àwọn fọ́nrán náà, ajẹ́rìí Baba Ijesha ní Adeleke ní kí ènìyàn tó le kó fọ́nrán tó wà lórí CCTV sí ibòmíràn, èèyàn nílò ẹ̀rọ kọ̀mpútà àti ẹ̀rọ ìkóǹkanpamọ́sí.
Adeleke ṣàlàyé pé lásìkò tí ènìyàn bá ń ṣe èyí àṣìṣe le wáyé , tí ènìyàn sì tún le ṣe àyípadà sí àwọn àkóónú inú rẹ̀.
Ó ní ó dá òun lójú pé wọ́n ti ṣe àyípadà sí àwọn àkóónú inú fọ́nrán náà èyí ló fà á tó fi ń sáré ju bó ti yẹ lọ.
- Ìyá ẹni ọdún 102 kéde ìpinnu rẹ̀ láti díje du ipò Ààrẹ Naijiria lọ́dún 2023
- Òní ní Oloye Christopher Adebayo Alao Akala yóò wọ káà ilẹ̀ lọ ní Ogbomoṣo
- Ẹnikẹ́ni tó bá tún fi ìyà jẹ òṣìṣẹ́ LASTMA l'Eko yóò fojú winá òfin- Ọ̀gá LASTMA
- Afurasí tọkọtaya ta ẹ̀yà ara ní ẹgbẹ̀rún lọ́nà àádọ́rin náírà- Ọlọ́pàá
- Wo àwọn ibùdó mánigbàgbé tó wà ní Ajaṣe ni orilé-èdè Benin Republic níbi tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Yorùbá ti lọ ṣàbẹ̀wò
- Ọmọ ọdún 18 dèrò àtìmọ́lé lórí ẹ̀sùn pẹ ó gún akẹgbẹ́ lọ́bẹ pa
- Àwọn tọ́ọ̀gì Aregbesola ló da wàhálà sílẹ̀ l'Osun - Ọlọ́pàá
- Ki lo ṣokunfa ikọlu to n waye si ẹni to ba wọ aṣọ Sunday Igboho tabi Yoruba Nation n'Ibadan?
Bákan náà ló fi kun pé àmì "ins" tó wà lábẹ́ fọ́nrán náà ni àmì ìdánimọ̀ "In Shot" áàpù kan tó wà fún ṣíṣe àtúnṣe àti àyípadà fọ́nrán.
Bẹ́ẹ̀ náà ló ní ẹ̀rọ alágbéká fóònù tàbí camcoder ni wọ́n ló láti fi ya fọ́nrán ifọrọwanilẹnuwo ni ago olopaa kìí ṣe CCTV nítorí bí àwòrán fọ́nrán náà daa ju ti foonu lọ.
Ṣùgbọ́n ó gbà pé àkóónú CCTV kò ṣé ṣe àyípadà sí tí wọ́n bá lò ó papọ̀ mọ́ Network Video Recording (NVR) àti (IP) gẹ́gẹ́ bí Dókítà Jide Martins tó peja ṣe sọ.
Kí ló ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn?
Nínú oṣù kẹrin, ọdún 2021 ni gbajúgbajà adẹ́rìnínpòṣónú Princess fẹ̀sùn kan Baba Ijesha pé ó bá ọmọ ọdún mẹ́rìnlá tó ń gbé lọ́dọ̀ òun sùn.
Oṣù méjì ni Baba Ijesha lò ní àtìmọ́lé kí wọ́n tó gba ìdáǹdè rẹ̀ nínú oṣù kẹfà.
Ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Baba Ijesha yìí fa awuyewuye lágbolé tíátà.

Oríṣun àwòrán, @Others
Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀
Òní ní Baba Ijesha tún fojú ba iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé o fí agídí bá ọmọdé lòpọ̀
Igbẹjọ gbajugbaja oserekunrin, Olanrewaju Omiyinka ti awọn ololufẹ rẹ mọ si Baba Ijesha tun ti foju ba ile ẹjọ lonii, ọjọ kẹtadinlogun, oṣu keji, ọdun 2022.
Lati nkan bii aago mẹwaa ni awọn oju to yẹ ti pe sib
Ohun ti Olanrewaju n jẹ ẹjọ naa le lori ni ẹsun ifipabanilopọ.
Ileẹjọ giga Ikeja High court ni igbejọ naa ti n waye bayii
Kini o n ṣẹlẹ nile ẹjọ bayii?
Gbogbo ijoko ti wa ni ikale bayii nile ẹjọ giga naa ti wọn n duro de Adajọ.
Won ti n ṣe atojọ awọn ẹri ti wọn fẹ gbe yẹwo lonii lori igbẹjọ Baba Ijesha ati Princess lori ọmọ to n gbe ọdọ Princess.

- Ẹ̀kún omi gbé èèyàn méjìdínlógójì lọ nílùú Petrópolis ní orílẹ́èdè Brazil
- Ẹ̀yin ará ìlú ẹ má bìnú, kìí ṣe pé a mọ̀ọ́mọ̀ kó epo tí kò dáa wọ Naijiria
- Gómìnà Zulum ṣe ìkìlọ̀ lórí ìdúnkookò ikọ̀ agbéṣumọ̀mí ISWAP sí Nàìjíríà
- Ìwádìí tó kúná ni a fẹ́ láti mọ̀ àwọn Onígbọ̀wọ́ olóògùn owó ní Oja Odan- Oba Oladiipo Oyebamiji
- Algeria yóò bẹ̀rẹ̀ sí ní san N41,000 fáwọn ọ̀dọ́ tí kò rí iṣẹ́ ṣe lóṣù tó ń bọ̀
- Amotekun Ondo gbẹ́sẹ̀lé ọkọ̀ àjàgbé tó ń kó àwọn ọ̀dọ́ 63 láti Gombe lọ sí Eko
- Kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn rẹ láti yé da àlááfíà ìlú láàmú- Ìjọba ìpínlẹ̀ Osun sí Aregbesola


















