Ìfipábánilòpọ̀: Ọlọ́pàá ní ọkùnrin tó fipá bá ọmọ ilé ìwé UNILAG lò, tún jí pátá rẹ̀

Obinrin kan to n roun pe wọn fi tipa ba lopọ

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Se ni awọn eeyan yanu sile, lai lee pa de nile ẹjọ to n gbọ awọn akanse ẹsun, nigba ti ẹjọ kan afurasi kan ti wọn lo fipa ba ọmọ ile iwe fasiti UNILAG meji lo pọ.

Nkem Ejelonu, to jẹ ọlọpaa to ṣe iwadi ọrọ naa, nigba ti ọmọbinrin naa lọ fẹjọ sun ni agọ ọlọpaa, tun salaye pe, John Otema, tii se olujẹjọ, tilẹ tun ji pata ọmọbinrin naa lọ.

Oṣu kini ọdun 2018 ni Ejelonu sọ fun ile ẹjọ wipe, Otema lu ọmọbinrin naa ni alubole, o fun-un lọrun, o tun ge jẹ nigba to fipa ba ọmọbinrin naa lo pọ ninu ọgba fasiti naa.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ko pẹ lẹyin rẹ ni wọn sọ pe afurasi naa tun ba ọmọbinrin keji lo pọ.

Ejelonu ni, oun ti lọ wa pata ati kọmu ọmọbinrin naa nibi ti Otema ti fipa baa lo, ṣugbọn nigba ti oun ko ri wọn nibẹ, oun tun lọ wa ile afurasi naa ni Bariga, Ṣugbọn ko ri pata naa nibẹ pẹlu.

Àkọlé fídíò, Demilade Adepegba: Mo má a ń gbàgbé fèrè ni, tí mo bá wà nílé ìwé

Adajọ Abiola Soladoye ti sun igbẹjọ naa siwaju di ọjọ kẹsan-an oṣu karun-un ọdun 2019, ti igbẹjọ yoo si tẹ siwaju.