Dare Adeboye: Ikú ẹ̀gbọ́n mi, ọ̀rẹ́ mi, ẹnìkejì mi, Dare kọ́ja bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n... -Leke Adeboye

Oríṣun àwòrán, Google
Leke Adeboye to jẹ aburo oloogbe Dare Adeboye ti sọrọ lori ohun ti oun yoo bẹrẹ si ni ṣe fun ẹbi ẹgbọn oun ni asiko yii to ti fi aye silẹ.
Ọjọ Kọkanla, Oṣu Karun un ni Dare Adeboye wọ ilẹ sun, lẹyin ti o doloogbe ni ẹni ọdun mejilelogoji ni Ọjọ Kẹrin, Oṣu Karun un, ọdun 2021.
Leke Adeboye lasiko to n sọrọ ni oun yoo sa gbogbo ipa oun lati ri i wi pe awọn ọmọ oloogbe naa ri itọju to peye.
- Ikú kò m'ọmọdé, kò màgbà, ẹ gbàdúrà fún ìdílé mi àti aya pẹ̀lú ọmọ olóògbé- Pásítọ̀ Adeboye
- Ọkọ mi kò kú rárá- Arabinrin Temiloluwa aya olóògbé Dare Adeboye
- Mi ò bú Baba Adeboye, mo kàn gégùn-ún fún àwọn tí kò ṣàtìlẹyìn fún Oduduwa Republic ni- Sunday Igboho
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Ṣé ǹkan oṣù rẹ ń dà hìì hìì lẹ́yìn tóó gba abẹ́rẹ́ àjẹsára Covid-19? Ẹ gbọ́ tuntun lẹ́nu àwọn Dókítà
- 'Nígbá tí a rí Baba Ijesha lónìí ní Panti, ohun tójú wa rí, ẹnu kò lè sọ o!'
Leke ni: ''Nibayii, mo mọ pe mo ni ọmọ mẹfa nitori mo bi mẹta, ẹgbọn mi si bi mẹta, ma a si ṣe itọju wọn.''
''Gbogbo nkan ti wọn ba n ṣe ni ma a ri wi pe mo peju-pesẹ sibẹ to fi mọ igba ti wọn ba n lọ ṣe ayẹwo ara wọn''
'Mo ti sọ fun iyawo mi pe: Awọn ọmọ rẹ ti da ti temi, ma a si sa gbogbo ipa mi lati wa nibẹ fun wọn.''

Oríṣun àwòrán, RCCG
Leke tun ni pe: ''Amọ mi o ni ṣe iṣe ajihinrere to gbe kalẹ nitori ọgbọn lati ṣe iṣẹ ihinrere rẹ yatọ si ti temi, ti ọpọlọpọ eniyan si fẹran rẹ ti o ba n waasu.''
'' Ti ẹgbọn mi ba n waasu, awọn eniyan ma n ho fun ayọ ni, amọ ti emi ba n waasu ko si ẹni ti yoo ho fun ayọ nitori mo ma n sọ otitọ ọrọ bii abata ti a na ni pọ̀pá ni, ẹnikẹni ni ọrọ mi le ta ba ni, kii ṣe bi ajihinrere.''
''Ohun gbogbo ni emi ati ẹgbọn mi ṣe papọ, to fi mọ ọjọ igbeyawo...''
- Bó ṣe nípasẹ̀ ọkada ni tàbí ọkọ̀ ojú omi tàbí láti inú ihò ilẹ̀, ẹ wá ọ̀nà láti fi Naijiria sílẹ̀- Pasitọ Paul Adefarasin
- Ẹ ò lè rí Covid-19 nínú ìjọ mi, ẹ má fi abẹ́rẹ́ rẹ̀ lọ̀ mí - Oyedepo
- Kàyèéfì! Wo ìdí tí àlùfáà ìjọ Aguda fi ń kó ère ìṣẹ̀nbáyé pamọ́?
- Ọkùnrin kan bí ẹgbẹẹgbẹ̀rún ni mi, àmọ́ o le darapọ̀ mọ́ ìwọ́de fún Baba Ijẹsha tí o ba tako ìfìyàjẹni
- Àwọn ọmọ Naijiria yóò rí akitiyan ìjọba láti yanjú ètò àbò tó mẹ́hẹ láìpẹ́ - Lai Mohammed

Oríṣun àwòrán, Leke Adeboye
Bakan naa ni Leke Adeboye sọ oriṣiriṣi ohun ti oun ati ẹgbọn oun jọ ṣe papọ lasiko ti wọn n dagba, titi awọn fi di ọdọ langba.
Leke ni ileẹkọ kan naa ni wọn jọ lọ lati ileẹkọ alakọbẹrẹ, girama, to fi mọ kikawe ni oke okun.
''Nigba ti mo gbọ wi pe ẹgbọn mi n lọ ka iwe ni oke okun ti ko si fẹ mu mi lọ, mo sọ fun pe ọkọ baalu rẹ yoo gbina ti ko ba mu mi dani.
- Òṣèré tíátà Yorùbá míràn tún kó sí gbaga ọlọ́pàá
- Ẹ̀yin ọmọ Naijiria, ẹ gbé ohùn àdúrà sókè nítorí ètò ààbò Naijiria - Buhari
- Eid al-Fitr: Wo àwọn ohun tó yẹ ki o ṣe sáájú ìrun Yidi fún ọdún ìtúnu ààwẹ̀
- Ogójì èèyàn ti pàdánù ẹ̀mí wọn nítorí ìjà tó ń wáyé láàrín Israel àti Palestine ní Lod
- Wo bí ìwọ́de Yomi Fabiyi nítorí ọ̀rọ̀ Baba Ijẹsha to wa ni àhámọ̀ ọlapàá ṣe n lọ nílùú Eko
- Ṣé èdì tàbí àsàsí leè sọ èèyàn di "Paedophile" tí kiní abẹ́ rẹ̀ kò ní gbé bì kan? - Elebuibon sọ̀rọ̀

Oríṣun àwòrán, Leke Adeboye
Leke tun ni: ''Ẹgbọn mi lo fi ẹjọ mi sun Baba Adeboye, ki o to di wi pe ẹmi naa tẹle e, ti a si jọ lọ ka iwe ni ileewe kan naa ni oke okun''
''Dare Adeboye jẹ ẹni to kun fun ọgbọn, ti kii ṣi ṣe imẹlẹ ni gbogbo nkan to ba n ṣe''

Oríṣun àwòrán, Leke Adeboye
Ọpọlọpọ igba ni awọn eniyan maa n sọ fun mi pe ṣe mi o le dabi ẹgbọn mi ni? amọ a yatọ si ara wa''
Leke Adeboye wa gbadura wi pe ọrun lo ja ju fun gbogbo onigbagbọ, ati wi pe oun gbadura wi pe bi Dare Adeboye ṣe pari daradara naa ni awọn yoo pari daradara ni ile aye.


















