Sunday Igboho on Adeboye: Àjìjàgbara, Sunday Adeyemo sọ pé àwọn èèyàn ṣi òun gbọ́ ni lórí ikú ọmọ Adeboye

Oríṣun àwòrán, livetimesng.com
Ọkan pataki lara awọn to n polongo idasilẹ Oduduwa Republic, Sunday Adeyemo 'Igboho' ti fesi si ẹsun ti awọn eeyan kan fi kan pe o fi iku ọmọ yọ Pasitọ Enoch Adeboye.
Opin ọsẹ to kọja ni fidio ifọrọwanilẹnuwo ti Igboho ṣe pẹlu ileeṣẹ agbohunsafẹfẹ ori ayelujara, Koiki Media, nibi to ti sọrọ nipa Adeboye, ati awọn olori ẹsin ti ko ṣe atilẹyin fun idasilẹ Oduduwa Republic.
Ninu fidio naa to tẹ BBC Yoruba lọwọ, ni ẹni to n fi ọrọ wa Igboho l'ẹnuwo ti sọ pe ko ki Anoch Adeboye lori iku ọmọ Baba Adeboye, Dare to di oloogbe l'ọsẹ to kọja.
Eyi waye lasiko ti Igboho n fi ọrọ idupẹ ranṣẹ si gbogbo awọn alatilẹyin rẹ.
Esi ti Sunday Igboho fọ ni pe ko si nkan to kan oun pẹlu iku ọmọ Adeboye.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post
Lẹyin naa lo tẹsiwaju lati sọ pe ẹgbẹlẹgbẹ ọmọ ijọ ni ijọ RCCG to jẹ ti Adeboye, eyi to yẹ ki pasitọ naa lo anfaani rẹ lati polongo idasilẹ orilẹ-ede Oduduwa fun wọn.
Ko tan sibẹ o, Igboho tun lo anfaani naa lati fi èpè ranṣẹ si gbogbo awọn 'ojiṣẹ Ọlọrun ti ko ba ṣe atilẹyin fun Yoruba Nation'.
O ni Ọlọrun yoo pa awọn iyawo ati ọmọ wọn.
- Wo orísun agbára tí Sunday Igboho gbójúlé tí ọwọ́ ẹnikẹ́ni kò fi le tẹ̀ ẹ́
- Àṣìṣe dókità ló pa Peju, ìbànújẹ́ dorí àgbà kodò- Funke Akindele
- Àyànmọ́ ló mú mi pàdé Princess, èrò wa jọra wọn- Iyabo Ojo
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Ẹ wo bí Leke Adeboye, àwọn ọ̀dọ́ ìjọ RCCG ṣe gẹ irun wọn láti bú ọlá fún Dare Adeboye tó papòdà
- Wo orúkọ mẹ́rìnlá tó làmìlaaka tí Lizzy Anjorin sọ ọmọ rẹ̀
Ọrọ naa fa awuyewuye ati ibinu laarin awọn ọmọ Naijiria, paapaa lori ayelujara.
Ọpọ lo si bu ẹnu ẹtẹ lu nkan ti Igboho sọ ninu fidio naa ti wọn n pin kiri lori ayelujara.
Ṣugbọn ni bayii, Ọgbẹni Igboho ti tun sọ ninu ifọrọwanilẹnuwo miran pe awọn eniyan ṣi oun gbọ ni.
O ni "ti mo ba dakẹ, wọn a ni mo ti gba rìbá. Mo tun sọrọ, wọn ni mo bu Baba Adeboye.
"Kilode ti ma a fi bu u?"
O ṣalaye pe wọn ṣi oun gbọ ni o, oun ko bu Adeboye, oun kan fi awọn to tako Yoruba nation gégùn-ún.
"Awọn to n dalẹ Yoruba ni mo fi gégùn-ún."
Yatọ si eyi, o sọ pe ka ni ọmọ Adeboye, Dare, to kú wa laye ni, "oun naa i ba ko ipa pataki ninu orilẹ-ede Yoruba wa tuntun".
Lẹyin naa lo gbadura pe ki oloogbe sun re.
Igba akọkọ kọ niyii ti ẹnu kun Sunday Adeyẹmọ lori ọrọ sisọ rẹ nipa awọn adari, lati igba to ti bẹrẹ ipolongo fun idasilẹ Oduduwa Republic.
Ni asiko diẹ sẹyin lo sọ ọrọ abuku nipa Ọọni Ile-Ifẹ, Ọba Adeyẹye Ogunwusi, ṣugbọn o pada tọrọ aforiji.
- Sunday Igboho ṣọ́ra ṣe, jẹ́ kí Seyi Makinde ṣiṣẹ́ tí òfin gbé le lọ́wọ́ - Ooni Ife
- Kábíyèsí Ooni ti forí jin Sunday Igboho lẹ́yìn tó túúbá- Ààfin Ile Ife
- Obìnrin bíi 1000 láti orílẹ̀èdè 37 bẹ Ọọ̀ni wò fún ìdásílẹ̀ orílẹ̀èdè Oduduwa
- Báwo ni ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Kayode Badru ṣe ṣẹlẹ̀ ní Celestial Church of Christ ni Eko? ẹ wo ohun tí a mọ̀!
- Sultan Sokoto ní káwọn mùsùlùmí wojú ọ̀run fún oṣù tuntun láti parí àwẹ̀


















