Dare Adeboye burial: Temiloluwa aya olóògbé Dare Adeboye ni ọkọ òun ń sùn ni

Oríṣun àwòrán, dareadeboye
Arabinrin Temiloluwa to jẹ aya oloogbe Dare Adeboye ni ọkọ oun ko bẹru iku rara.
O fidi ọrọ yii mulẹ pe ọkọ oun ko ku nibi eto isin idagbere to waye nile ijọsin House of Favour ni Redemption Camp ni Mowe ni irọlẹ ana ojọ Aje.
Temiloluwa ṣalaye pe oun ni aridaju pe ọrun rere ni Dare Adeboye ti lọ sinmi nitori pe eniyan ọtọ ni.
Bakan naa lo rọ awọn eniyan ti ko tii ni Jesu laye wọn tabi ti wọn ti pada se\yin lati pada sile lọdọ Olugbala wọn nitori iru ọjọ bayii ti wọn a sun ti wọn ko ni ji mọ.
- Ìjọba dá òfin kónlé-ó-gbélé lórí àjàkálẹ̀ àrùn covid-19 padà
- Ènìyàn 49 ló tún ṣẹ̀ṣẹ̀ lùgbàdí ààrùn Coronavirus ní Naijiria
- Orílẹ̀-ède UK ti gbégi lé àwọn arìnrìàjò láti Nàìjíríà nítorí…
- Òní ni àṣekágbá ètò ìsìnkú olóògbé Dare Adeboye ni Redemption Camp
- Ẹ̀mí ọlọ́pàá mẹ́tàlá ló sọnù lópin ọ̀sẹ̀ lọ́wọ́ àwọn "unknown gunmen"
- Ṣé ẹ rántí àwọn ìkọlù tó ti wáyé ní ilé ìjọba rí? Àwọn rèé

Oríṣun àwòrán, dareadeboye
Mi ó ṣọ̀fọ̀, mo sọkún nítorípé... - Ìyàwó olóògbé Dare Adeboye sọ̀rọ̀ níbi ìsìn idágbére ọkọ rẹ̀
Wo àwọn ìdílé Dare Adeboye níbí ètò ìsìn ìdágbére rẹ tó bẹrẹ lana
Ero ko gba ẹsẹ nibi eto isin idagbere oloogbe Pasitọ Dare Adeboye to jẹ́ ọmọkunrin kejiadari ijọ Redeemed Christian Church of God, RCCG.
Gbogbo ẹbi, ara ọrẹ ati ojulumọ lo peju pesẹ sibi isin naa to bẹrẹ ni dede ago mẹrin irọlẹ ọjọ Aje, ọjọ kẹwa oṣu karun.
Iyawo oloogbe, Temiloluwa ni oun ko ṣọfo tori oun gbagbọ pe lootọ ni ọk oun jẹ onigbagbọ tootọ ti inu oun si dun.
- Òní ni àṣekágbá ètò ìsìnkú olóògbé Dare Adeboye ni Redemption Camp
- Mi ò bú Baba Adeboye, mo kàn gégùn-ún fún àwọn tí kò ṣàtìlẹyìn fún Oduduwa Republic ni- Sunday Igboho
- Ẹ wo bí Leke Adeboye, àwọn ọ̀dọ́ ìjọ RCCG ṣe gẹ irun wọn láti bú ọlá fún Dare Adeboye tó papòdà
- Ìjọba dá òfin kónlé-ó-gbélé lórí àjàkálẹ̀ àrùn covid-19 padà
- Ènìyàn 49 ló tún ṣẹ̀ṣẹ̀ lùgbàdí ààrùn Coronavirus ní Naijiria
- Ẹ̀mí ọlọ́pàá mẹ́tàlá ló sọnù lópin ọ̀sẹ̀ lọ́wọ́ àwọn "unknown gunmen"
Mi o sofo rara mo sọkun tori pe o fi mi silẹ ni - Iyawo Oloogbe
Nigba ti asiko rẹ to lati sọrọ, Temiloluwa aya oloogbe Pasitọ Dare Adeboye fi ọkan igbagbọ ke Halleluyah pẹlu gbogbo ero to wa ninu gbọngan.
"O sun ni ko ku, ko ku mo si mọ, o da mi loju pe ni owurọ ọjọ ajinde, yoo jinde a o si ri i ninu ogo".
Iyawo oloogbe ni o da oun loju pe igbagbọ rẹ ninu Jesu daju.
"O sọ fun mi pe, bi mo(Dare) ba ku lonii, mo mọ pe mo ti ṣe ohun ti Ọlọrun ni ki n ṣe".
Iyawo rẹ ni o da oun loju pe o wa ni ọrun to si fi akoko na waasu fun awọn to wa nibẹ pe ti ko ba da wọn loju ibi ti wọn n lọ lẹyin aye, ki wọn yipada ki wọn gba Jesu gbọ.
- Ẹ wo bí Leke Adeboye, àwọn ọ̀dọ́ ìjọ RCCG ṣe gẹ irun wọn láti bú ọlá fún Dare Adeboye tó papòdà
- A kò ní pe Ọlọ́run ní ẹjọ́ lórí ìkú ọmọ wa, Dare Adeboye - Ẹbí Adeboye
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Báwo ni ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Kayode Badru ṣe ṣẹlẹ̀ ní Celestial Church of Christ ni Eko? ẹ wo ohun tí a mọ̀!
- Ìyàwó Adeboye gbàdúrà fún Nàìjíríà ní ìgbà akọkọ tó fara hàn lẹ́yìn ikú ọmọ wọn, Dare
- Ẹbí Adeboye kéde bí ìlànà ikú Pásítọ Dare yoo ṣe lọ
Ẹni to bọwọ to tẹriba ni Pasitọ Dare - Osinbajo

Oríṣun àwòrán, dareadeboye
"Deeti ọjọ kan naa ni emi ati ẹgbọn mi ṣe igbeyawo, gbogbo ibi to lọ ni mo n gba tọ ọ lẹyin ni kekere"

Oríṣun àwòrán, dareadeboye
Aburo oloogbe to tun jẹ abigbẹyin baba Adeboye iyẹn Leke Adeboye ni gbogbo nkan lo fẹrẹ jẹ pe awọn jọ n ṣe papọ to bẹẹ to jẹ wipe bi igbin fa ikarahun a tẹle e ni ọrọ oun ati ẹgbọn oun Dare lati kekere.
"Ileewe alakọbẹrẹ titi de fasiti kan naa la jọ lọ, ori bẹẹdi onirin oke ati isalẹ kan naa lemi atirẹ n sun si".
Leke to gbiyanju lati ma jẹ ki omije bọ loju rẹ ṣa ara jọ to si sọ diẹ lara igbesi aye oloogbe Dare Adeboye.
Koda Leke ni deeti ọjọ ti ẹgbọn oun Dare ṣeyawo loun naa mu ni ọdun ti oun fẹ ṣeyawo ti awọn si tun fẹẹ bimọ tẹlera.
O ni bii kii ba ṣe iṣẹ iranṣẹ to pe awọn pada wa si Naijiria ni, iwe ti oun ati ẹgbọn oun lọ ka niilẹ Gẹẹsi ko ba ti mu awọn ti ọmọ adulawọ akọkọ to jẹ minisita tori ẹgbọn jẹ oye adari ọmọ ileewe girama lọhun to si jẹ pe oun ni ọmọ ilẹ Afirika akọkọ to ṣe iru rẹ.

Oríṣun àwòrán, www.dareadebooye
Bakan naa, iyawo aburo oloogbe, Leke Adeboye lo kọkọ ka iwe kika bibeli akọkọ ninu isin naa gẹgẹ bo ṣe ka lati inu iwe Kọrinti kini ori kẹẹdogun to sọrọ nipa igbasoke awọn ayanfẹ pe ...kii se gbogbo wa lao sun... iku oro rẹ da, isa oku iṣẹgun rẹ da..."

Oríṣun àwòrán, Www.dareadeboye
Ireoluwa Adeboye - Ọmọ Oloogbe

Oríṣun àwòrán, Adeboye
"Mo fẹ ka ẹsẹ Bibeli yii nitori baba mi to ti wa lọrun".
Ireoluwa ka lati inu iwe Tesalonika kini ori kẹrin lati ẹsẹ ikẹtala ninu eyi to ti sọ wipe "...nitoripe Oluwa fura r yoo sọkalẹ lati Ọrun wa pẹlu igbe ati ti awọn Angẹli, awọn oku ninu Krisiti ni yoo si kọkọ ji dide lọ pade rẹ... nitorinaa ẹ ma tu ara yin ninu".

Oríṣun àwòrán, dareadeboye

Oríṣun àwòrán, dareadeboye

Oríṣun àwòrán, dareaadeboye

Oríṣun àwòrán, dareadeboye

Oríṣun àwòrán, dareadeboye

Oríṣun àwòrán, dareadeboye













