Covid-19 in Nigeria: Ìjọba dá òfin kónlé-ó-gbélé lórí àjàkálẹ̀ àrùn covid-19 padà

Awọn oṣiṣe\NCDC

Oríṣun àwòrán, Twitter/NCDC

Ijọba apapọ orilẹede Naijiria ti da ofin konle-o-gbele pada lori ati dena ajakalẹ arun coronavirus.

Ọkan lara awọn oludari igbimọ PTF to n ri si ati dena ajakalẹ arun naa ni Naijiria, Dokita Mukhtar Mohammed lo fọrọ yii lede lọjọ Aje.

O ṣalaye pe ijọba ti da ofin konle-o-gbele to wa tẹlẹ laarin ago mejila alẹ si ago mẹrin aarọ pada kaakiri gbogbo ipinlẹ to wa ni Naijiria.

Bakan naa lo ṣalaye pe lati alẹ ọjọ Iṣẹgun, gbogbo ile ijo, gbọngan idaraya yoo di titi pa.

O tun fikun ọrọ rẹ pe ipejọpọ awọn eeyan ko gbọdọ ju aadọta lọ mọ lati asiko yii lọ

''Ẹnikẹni ti ko ba wọ ibomu ko ni lanfaani lati wọ ileeṣẹ ijọba kankan.

Lori ayelujara ni ipade awọn ileeṣẹ ijọba yoo ti maa waye bayii.

Àkọlé fídíò, Alara tí Ilara Epe: Òjò gbọ́dọ̀ rọ̀ lásìkò ọdún Ẹlẹ́gba ni ìlú Epe- Oba Olufolarin Ogunsan

Awọn ti o ṣe pataki fun lati rinrin ajo lọ si oke okun nikan lo yẹ ki wọn rinrin ajo lọ si ilẹ okeere bayii,'' Dokita Mohammed lo ṣalaye bẹẹ.

Amọ, o sọ pe awọn eeyan yoo ṣi maa lanfaani lati rinrin ajo lati ipinlẹ kan si omiran kaakiri Naijiria.