Ondo kidnap: Amotekun Ondo ju afurasí ajínigbé mẹ́rin s'átìmọ́lé, dóòlà àwọn tí wọ́n jígbé

Oríṣun àwòrán, Amotekun Ondo
Ọjọ gbogbo ni ti ole, ọjọ kan bayii ni ti oloun.
Ẹṣọ Amotekun ipinlẹ Ondo lo ti fi ọwọ ofin mu awọn afurasi ajinigbe mẹrin niluu Akure.
Ọga agba Amotekun nipinlẹ Ondo to ba BBC Yoruba sọrọ, Oloye Adetunji Adeleye ṣalaye pe oju ọna Akure si Oda lawọn afurasi ọhun ti ji awọn eeyan gbe lọ.
- Wo orísun agbára tí Sunday Igboho gbójúlé tí ọwọ́ ẹnikẹ́ni kò fi le tẹ̀ ẹ́
- Àṣìṣe dókità ló pa Peju, ìbànújẹ́ dorí àgbà kodò- Funke Akindele
- Emmanuel Abina, ọmọ Olùdarí ìjọ GOFAMINT, Elijah Abina jáde láyé lẹ́yìn ikú ìyàwó rẹ̀
- Wo orúkọ mẹ́rìnlá tó làmìlaaka tí Lizzy Anjorin sọ ọmọ rẹ̀
- Ẹ wo bí Leke Adeboye, àwọn ọ̀dọ́ ìjọ RCCG ṣe gẹ irun wọn láti bú ọlá fún Dare Adeboye tó papòdà
- Egúngún bá òṣèrébìnrin lòpọ̀ nínú eré, àwọn Eléégún yarí
Oloye Adeleye sọ pe ẹṣọ Amotekun doola awọn eeyan tawọn afurasi ọhun jigbe lọ.
Ọga agba Amotekun ni ileeṣẹ ọlọpaa naa ṣiṣẹ pọ pẹlu awọn ẹṣọ Amotekun lati ri pe ọwọ tẹ awọn afurasi naa.
''Lẹsẹkẹsẹ ti iṣẹlẹ ọhun ṣẹlẹ ni a fi ọrọ naa to ileeṣẹ ọlọpaa ati ajọ ọtẹlẹmuyẹ DSS ipinlẹ Ondo.
Gbogbo ẹṣọ eleto abo nipinlẹ Ondo ni a jọ ṣiṣẹ papọ lori ati mu awọn afurasi naa,'' Oloye Adeleye ṣalaye.
O fikun ọrọ rẹ pe awọn afurasi mẹrin naa si wa ni atimọle ẹṣọ Amotekun nigba ti iwadii ṣi n lọ lọwọ.
Oloye Adeleye ni o ṣeeṣe ko jẹ wi pe lati atimọle ẹṣọ Amotekun lawọn afurasi naa yoo gba lọ sile ẹjọ.
Amọ, o sọ pe iwadii ṣi n lọ lọwọ, ati pe abajade iwadii lo maa sọ bo ya awọn maa fawọn afurasi naa lọ sọdọ awọn ọlọpaa.
- Báwo ni ìṣẹ̀lẹ̀ ikú Kayode Badru ṣe ṣẹlẹ̀ ní Celestial Church of Christ ni Eko? ẹ wo ohun tí a mọ̀!
- Sultan Sokoto ní káwọn mùsùlùmí wojú ọ̀run fún oṣù tuntun láti parí àwẹ̀
- Ìjọ Kátólìkì, ẹ jèbùrẹ́, ọmọdé ló ṣe èmi àtàwọn ọmọ ìjọ mi- Father Mbaka
- À ń ṣe ìwádìí lọ́wọ́ bí ''candle'' ṣe pa Kayode Badru ní ìpínlẹ̀ Eko - Ọlọ́pàá
- Àyànmọ́ ló mú mi pàdé Princess, èrò wa jọra wọn- Iyabo Ojo














