Pastor Paul Adefarasin: Bí Naijiria kò bá rọrùn láti gbé ẹ gba orílẹ̀-èdè míì lọ

Oríṣun àwòrán, @Adefarasin
Bó ṣe nípasẹ̀ ọkada ni tàbí ọkọ̀ ojú omi tàbí láti inú ihò ilẹ̀, ẹ wá ọ̀nà láti fi Naijiria sílẹ̀- Pasitọ Paul Adefarasin
Oluṣọagutan agba ati oludasilẹ ijọ House on The Rock, pasitọ Paul Adefarasin ti gba awọn ọmọ ijọ rẹ nimọran pe ki wọn fi Naijiria silẹ lọ ilẹ miran ti aye rẹ ba ṣi silẹ.
Ninu iwaasu rẹ to ṣe lọjọ Aiku lo ti sọ ọrọ naa nibi to ti sọ pe awọn to ti n ṣejọba Naijiri bọ latẹyinwa ati lọwọ yii ko kọbi ara si bi nnkan ṣe lọ.
- Ẹni tó bá ní láàkàyè, a mọ ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn, àwà ti kọ lẹ́tà, èsì t'Ọ́lọ́pàá sì fún wa rèé - Yomi Fabiyi
- Àwọn adigunjalè gbìyànjú àti fọ́ ile olórí àwọn òṣìṣẹ́ lọ́fíìsì ààrẹ.
- Àyànmọ́ ló mú mi pàdé Princess, èrò wa jọra wọn- Iyabo Ojo
- Wo orúkọ mẹ́rìnlá tó làmìlaaka tí Lizzy Anjorin sọ ọmọ rẹ̀
- Ẹ wo bí Leke Adeboye, àwọn ọ̀dọ́ ìjọ RCCG ṣe gẹ irun wọn láti bú ọlá fún Dare Adeboye tó papòdà
- Sultan Sokoto ní káwọn mùsùlùmí wojú ọ̀run fún oṣù tuntun láti parí àwẹ̀
- Ìjọ Kátólìkì, ẹ jèbùrẹ́, ọmọdé ló ṣe èmi àtàwọn ọmọ ìjọ mi- Father Mbaka
- Ìjọba dá òfin kónlé-ó-gbélé lórí àjàkálẹ̀ àrùn covid-19 padà
Pasitọ naa ni bo tilẹ jẹ pe oun ni igbagbọ pe Naijira ṣi maa dara, oun ti wa wọrọkọ fi ṣ'ada lati fi Naijiria silẹ ti nnkan ba pada yiwọ.
O ni "Mo mu ikinni wa fun yin lati ọdọ pasitọ Ifeanyi to n ṣeto ọna abayọ wa… mo mọ pe ẹ ni igbagbọ o, emi naa ni igbagbọ, ṣugbọn mo ti wa abayọ lati fi orilẹ-ede yii silẹ."
Adefarasi ṣalaye pe oun le ṣe iwaasu fun awọn ọmọ ijọ naa lati ibikibi lorile¬̣-ede agbaye pẹlu imọ ẹrọ, nitori naa lo ṣe ṣe pataki ki awọn eeyan naa tete wa ọna abayọ lati sa kuro ni Naijiria nitori gudugbẹ to ṣeeṣe ko ja lọjọ iwaju.
O ni "Bo ṣe nipasẹ ọkada ni tabi ọkọ oju omi tabi lati inu iwo ilẹ, ẹ wa ọna abayọ lati fi Naijiria silẹ nitori awọn adari Naijiria ko ni afojusun rere fun araaalu."
Pasitọ naa tun ke si awọn adari ijọba ni Naijiria lati tun Naijiria ṣe ki ogun abẹle keji ma baa bẹ silẹ.
- Mi ò bú Baba Adeboye, mo kàn gégùn-ún fún àwọn tí kò ṣàtìlẹyìn fún Oduduwa Republic ni- Sunday Igboho
- Èèyàn 28 kú nínú ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi tó dànù ní ìpínlẹ̀ Niger
- Àwọn agbébọn ya wọ mọ́ṣáláàṣí, wọ́n gbe èèyàn 40 lọ lásìkò àdúrà Tahajjud
- Amotekun Ondo ju afurasí ajínigbé mẹ́rin s'átìmọ́lé, dóòlà àwọn tí wọ́n jígbé
- À ń ṣe ìwádìí lọ́wọ́ bí ''candle'' ṣe pa Kayode Badru ní ìpínlẹ̀ Eko - Ọlọ́pàá
- Àwọn adigunjalè gbìyànjú àti fọ́ ile olórí àwọn òṣìṣẹ́ lọ́fíìsì ààrẹ.
Gẹgẹ bo ṣe sọ "Iṣoro Naijiria ti pọ ju ti tẹlẹ lọ, o si yẹ ki a ṣe iwadii awọn iṣoro naa lati ipinlẹṣẹ igba ti a gba ti ominira, bi bẹẹ kọ, ko si ohun ti a le ṣe lati yanju iṣoro ti a n koju."
Pasitọ naa pari ọrọ rẹ pe ko si orilẹ-ede kankan to le farada ogun abẹle meji.
Lẹyin naa lo rọ awoon adari lati pe ipade apero ki wọn si jiroro bi Naijiria yoo ṣe ni ilọsiwaju lawujọ awọn akẹgbẹ rẹ.
Ọpọ awọn ọmọ Naijiria lo ti bẹrẹ si n fi erongba wọn lede lori ọrọ ti pasitọ naa sọ.
Bi awọn kan ṣe n kiin lẹyin pe ootọ ọrọ lo sọ lawọn mii n sọ pe kii ṣe irufẹ iwaasu to yẹ ko maa ṣe fun awọn ọmọlẹyin rẹ niyẹn.
- Èèyàn 28 kú nínú ìjàmbá ọkọ̀ ojú omi tó dànù ní ìpínlẹ̀ Niger
- Àwọn agbébọn ya wọ mọ́ṣáláàṣí, wọ́n gbe èèyàn 40 lọ lásìkò àdúrà Tahajjud
- Amotekun Ondo ju afurasí ajínigbé mẹ́rin s'átìmọ́lé, dóòlà àwọn tí wọ́n jígbé
- Ọkọ mi kò kú rárá- Arabinrin Temiloluwa aya olóògbé Dare Adeboye
- Ẹ̀mí ọlọ́pàá mẹ́tàlá ló sọnù lópin ọ̀sẹ̀ lọ́wọ́ àwọn "unknown gunmen"
- Òní ni àṣekágbá ètò ìsìnkú olóògbé Dare Adeboye ni Redemption Camp














