Gani Adams ṣe ọdún Olókun, ó fi òkò ọ̀rọ̀ ránṣẹ́ sí ààrẹ Buhari

Oríṣun àwòrán, Aareganiadams/Instagram
Aarẹ Ona Kakanfo ilẹ Yoruba, Iba Gani Adams ti fi aidunnu rẹ han lori bi ẹnu ibode Nigeria pẹlu Benin, Seme, ṣe ṣi wa ni titi pa.
Adams sọ pe bi ijọba ṣe ti ibode naa pa lati ọdun 2019 jẹ ifiyajẹni fun awọn eniyan Iwọ Oorun Gusu Naijiria, ati akoba fun ọrọ aje.
Oṣu Kọjọ, ọdun 2019 ni ijọba Aarẹ Muhammadu Buhari ti ẹnu ibode naa pa "lati le fi opin si kiko ọja ati nkan ijagun oloro wọ Naijiria".2
Àwọn iròyin tì ẹ le ní ìfẹ̀ síí:
- Nnkan ìtìjú gbàá ni bí wọ́n ṣe já ọgbà ẹ̀wọ̀n l'Oyo - Iba Gani Adams
- Ọmọ onílẹ̀ mẹ́ta kó sí páńpẹ́ ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn
- Darandaran kan rí ẹ̀wọ̀n gbéré he ní Ekiti
- Nǹkan yan! Pásítọ̀ dáwọn ọmọ ijọ̀ dùbúlẹ̀ lórí pẹ̀pẹ́, ó ń nà wọ́n pẹ̀lú bẹ́lítì
- Bí ìgbẹ́jọ́ Naira Marley ṣe lọ lọ́jọ́ Iṣẹ́gun rèé
- Boko Haram fi tipa fẹ́ mi fún ọkọ àmọ́ ìfẹ́ rẹ̀ gbóná lọ́kàn mi ni ń kò fi sá kúrò
- Kí ló dé tí Fayemi kò fí tẹ̀lé àwọn Gómìnà Yorùbá lọ kí Tinubu nílé?
- Wo àwọn gbajúmọ̀ míràn yàtọ̀ sí Tiwa Savage tí ọ̀rọ̀ fídíò ìbálòpọ̀ wọn ti bọ́ sí orí ayélujára ...
- Ó ṣe é ṣe ká má kópa nínú ìdìbò 2023 tí àtúntò Naijiria kò bá wáyé - Afenifere
- Àwọn amòfin ní ẹ̀yà Igbo dara pọ̀ mọ́ ẹjọ́ tí àwọn àgbààgbà Àríwá pè lórí Kanu àti IPOB
Ọjọru ni Adams sọ ọrọ yii lasiko to kopa nibi ọdun Olokun to waye ni Suntan Beach, nilu Badagry.
Iba Adams sọ pe titi ibode naa pa fun ọdun mẹta jẹ nkan to buru fun orilẹ-ede bi i Naijiria ati ọrọ aje rẹ.
O ni ijọba sọ pe nitori eto aabo ni oun fi ṣe bẹẹ, ṣugbọn "ko ti i si ayipada rere kankan ninu ipenija eto aabo".
"Lai jẹ pe ogun n waye, titi ibode naa pa jẹ iwa ika si awọn eniyan ilẹ Yoruba. Ipa ti yoo si ni lara ọrọ aje Naijiria paapaa ko ni i kere."
Gani Adams sọ pe oun rọ ijọba Naijiria pe ko tete ṣi ibode Seme pada nitori ipa pataki to n ko ninu idagbasoke ọrọ aje Naijiria ati awọn eniyan rẹ.

















