2023 General Elections: Èmi ni mo kájúẹ láti di Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà – Tinubu

Bola Tinubu

Oríṣun àwòrán, Screen shot

Àkọlé àwòrán, Bola Tinubu

Adarí àpapọ̀ fún ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC), Bola Tinubu ti ní òun ni ẹni tó tọ́ láti jẹ Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní kété tí Ààrẹ Muhammadu Buhari bá ti gbésẹ̀.

Tinubu ní òun ní gbogbo ìgboyà àti àmúyẹ tí Ààrẹ tó le mí àyípadà ọ̀tun àti ìdàgbàsókè tó lòòrìn bá orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

Níbi ìpàdé àti ìjíròrò ọlọ́jọ́ kan èyí tí Tinibu ṣe pẹ̀lú àwọn Abẹnugan àti àwọn ìgbákejì Abẹnugan ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin ẹgbẹ́ òṣèlú APC tó wáyé ní ìpínlẹ̀ Eko ló ti ṣíṣọ lójú ọ̀rọ̀ yìí.

Ó sọ wí pé ìlọsíwájú àti ìdàgbàsókè orílẹ̀ èdè Nàìjíríà wà lọ́wọ́ bí àwọn adarí bá ṣe lè ronú àti bí wọ́n bá le ṣe jí gìrì sí ojúṣe wọ́n sí.

Àkọlé fídíò, Oluyemisi Orisabiyi: Ẹ̀ẹ̀mẹta péré làwọn òṣìṣẹ́ KAI bẹ̀ mí wò, mo kọ̀wé sí wọn lái rí èsì

"Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nílò mi gẹ́gẹ́ bí èmi náà ṣe nílò Nàìjíríà nítorí mo jẹ́ ẹni tó le ronú tó sì ní ìgboyà láti mú àyípadà ọ̀tun bá a."

"Ẹni tó ní ìgboyà ní Ọlọ́run dá mi tó sì ń ṣe iṣẹ́ fún mi, mo sì fẹ́ lò ó fún orílẹ̀ èdè Nàìjíríà náà."