Maiduguri IGP son wedding: Èrò àwọn ọmọ Nàìjíríà ṣọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ bí wọ́n ṣe rí Abba Kyari, Obi Cubana níbi ìgbéyàwò ọmọ ọ̀gá ọlọ́pàá Alkali Baba

Oríṣun àwòrán, Others
Bi o ṣe n ṣepo, ko ṣọra.
Ohun to kọ iwaju si ẹnikan, ẹyin lo kọ si elomii ni ọrọ awọn ero to wa sibi ayẹyẹ igbeyawo ọmọ ọga agba awọn agbofinro ni Naijiria to waye ni ana, ọjọ Satide, ọjọ Kọkandinlọgbọn, oṣu Kinni, ọdun 2022 ni Maiduguri ni ipinlẹ Bornu.
Ana ode yii ni Maina Alkali to jẹ ọmọkunrin Baba Alkali to jẹ ọga agba pata fun gbogbo awọn ọlọpaa ni Naijiria ṣe igbeyawo pẹlu ololufẹ rẹ ni Maiduguri.
Aafin Shehu ti borno, Abubakar El-Kanemi ni Maiduguri ni eto igbeyawo naa ti waye ni olu ilu Bornu ni ariwa Naijiria.
- Ta ni Tunji Disu ti wọ́n kéde láti rọ́pò Abba Kyari?
- Ọwọ́ FBI yóò tẹ Abba Kyari, òǹyẹ̀ kankan kò lè yẹ̀ ẹ́ - Femi Falana
- Ọ̀gá Àgbà Ọlọ́pàá, ẹ ríi dájú pé ẹ tú gbogbo àṣírí nípa ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan Abba Kyari àti Hushpuppi - Àpapọ̀ Agbẹjọ́rọ̀
- Wo àmí ẹ̀yẹ tí Abba Kyari tí gba gẹ́gẹ́ bí ògbóǹtagìrì ọlọ́pàá kí wọ́n tó fi ẹ̀sùn ìwà àjẹbánu kàn án
- Hushpuppi: Ẹ lọ gbé Abba Kyari wá jàǹtò láti sọ tẹnu rẹ̀ - Ilé ẹjọ́ Amẹrika
- Ọlọ́pàá mẹ́rin d‘òkú lásìkò tí wọn wọ̀yá ìjà pẹ̀lú agbébọn
- Kíni àwọn ojúṣe olórí àwọn òṣìṣẹ́ ààrẹ̀ Nàìjíríà?
Awon wo lo wa sibi igbeyawo naa?
Ọpọlopọ gbajumọ lo peju sibi eto igbeyawo naa ni ipinle Bornu.
Die lara wọn ni Abba Kyari to jẹ olori ikọ ọtẹlẹmuyẹ idahun pajawiri ti ẹnu n kun lati ọdun to kọja pe o gba abẹtẹlẹ to pọ to si di wahalaKí ni yóò ṣẹlẹ̀ sí gbajúmò ọlọ́pàá, Abba Kyari tí wọ́n kó pọ̀ mọ́ "rógà" pẹ̀lú Hushpuppi?
Awọn mii to tun wa nibi igbeyawo naa ni: Obinna Iyiegbu ti ọpọ mọ si Obi Cubana to di gbajugbaja sii lẹyin to sinku iya rẹ pẹlu ọpọlọpọ maalu to n jẹ ki araye kigbe kiri Wo ǹkan mẹ́ẹ̀dògún tó yẹ kí o mọ̀ nípa olówó ayé Obi Cubana
- EFCC gbé bàbá olówó Obi Cubana
- Wàhálà ìjọba Nàìjíríà ló lé mi kúrò nílùú Abuja lọ Portharcourt tọ́rọ́ mi fi dayọ̀- Obi Cubana
- Iná ẹlẹ́tíríìkì gbé èèyàn kan ni ilé ijó Obi Cubana l'Abuja, ó fò ṣánlẹ̀ kú
- Àwọn nǹkan mẹ́ta tí a kò tíì mọ̀ nípa Covid-19 lẹ́yìn tí àrùn náà bẹ́ sílẹ̀ rèé
- Nkan dẹnu kọlẹ̀ ní àwọn agbègbè kan ní America nítorí ìjì líle
- Èèyàn méjì dèrò ọ̀run nínú ìkọlù ọlọ́pàá àtàwọn akẹ́kọ̀ọ́ ẹlẹ́gbẹ́ òkùnkùn Kwara Poly
Gomina ipinlẹ Borno, Babagana Zulum naa wa lara awọn to peju peṣẹ sibẹ.
Gomina ipinlẹ Yobe ati Jigawa, Mai Mala Buni ati Badaru Abubakar naa ba wọn peju yọ ayọ igbeyawo ọmọ Baba Alkali naa.

Oríṣun àwòrán, @Abba Kyari facebook
Kini o bi ẹjọ lori ayelujara lori igbeyawo ọmọ ọga ọlọpaa naa?
Ni kete ti awọn ọmọ Naijiria ti n ri aworan pe abba Kyari to n koju ẹsun riba gbigba naa wa nibé ni awọn ọmọ Naijiria ti n sọrọ lori ayelujara.
Ko pẹ si asiko igbeyawo yii naa ni Abba Kyari si ko fọto to pọ soju opo facebook rẹ ni eyi ti awọn eeyan si bẹrẹ si ni sọ di koko ijiroro lori ayelujara.
Bi awọn kan ṣe n ni ko buru ni awọn míì ní ko yẹ ko ri bẹẹ.

Oríṣun àwòrán, others
Awon mii to tun wa nibi igbeyawo Alkali naa ni Aarẹ awon Asofin ni Abuja, Ahmad Lawan, Minista fun iriina oju ofurufu, iyẹn Hadi Sirika, Aliko Dangote to jẹ olowo oniṣowo ilẹ Adulawo ati Aminu Ahmed, oludari ileeṣẹ Tiamin.

Oríṣun àwòrán, Others
Awọn orukọ wo ni wọn n sọ nipa wọn?
Ni kete ti Abba Kyari ati awọn mii ti ṣafihan awọn aworan ti wọn ya nibi eto igbeyawo ọmọ Alkali Baba naa ni awọn eeyan ti n sọrọ lori ayelujara ti orukọ awọn mii si ti n jade.
Orukọ bii Igbalode Ramoni ti ọpọ mọ si Hushpuppi ti o fẹsun kan Abba Kyari naa ti n jade pẹlu.
Hushpuppi lo n jẹ ẹjọ lọwọ ni orilẹ-ede America lẹyin ti United States of America's Federal Bureau of Investigation fẹsun kan an.
Bakan naa ni orukọ Obi Cubana naa tun n jade pelu irufẹ eto isinku alarinrin to ṣe fun iya rẹ seyin.
- Lanre Gentry, ọkọ Mercy Aigbe tẹ́lẹ̀ sọ̀rọ̀ sókè lórí ìgbéyàwó aya rẹ̀ àná
- Àlàyé rèé lórí ìròyìn tó ní Buhari ti kú, Jubril Sudan ló ń darí Nàíjíríà
- Iléeṣẹ́ ìròyìn BBC ṣe ìfilọ́lẹ̀ àmì ẹ̀yẹ Komla Dumor
- Afenifere ń gbèrò láti dá ẹgbẹ́ òṣèlú sílẹ̀, àgbà Yoòbá kan ní àbùkù ni yóò gbẹ̀yìn rẹ̀
- Kí ló dé tí ológun ń yẹ àga ìjọba mọ́ alágbádá nídìí l‘Áfíríkà?
- Ìgbẹ́jọ́ Baba Ijesha forí sánpọ́n, agbẹjọ́rò rẹ̀ kò yọjú sílé ẹjọ́
- Timothy Adegoke yóò wọ ilẹ̀ sùn lọ́jọ́ Àbámẹ́ta, bí ìsìnkú rẹ̀ yóò ṣe lọ rèé














