Baba Ijesha: Iléèṣẹ́ ọlọ́pàá ní wọ́n le gba béèlì ẹ̀ṣùn bíbá ọmọdé tage àmọ́ wọn kìí gba béèlì bíbá ọmọdé lòpọ̀

Ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko ti kede pe oun ko ni gba beeli gbajumọ osere tiata ti wọn fẹsun kan pe o fi tipa ba ọmọ ọdun mẹrinla lopọ, ti ọpọ eeyan mọ si Baba Ijesha.
Kọmisana fun ileesẹ ọlọpa nipinlẹ Eko, Akeem Odumosu lo kede bẹẹ lasiko ipade akọroyin to se ni olu ileesẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko lọjọ Ẹti.
Odumosu, ẹni to sọrọ lori iwọde tawọn ajafẹtọ ẹni kan se wa sọdọ rẹ lati tako beeli Baba Ijesha tun ni, ẹsun meji ni wọn fi kan afurasi naa, idi si niyi ti yoo si se wa ni ahamọ ọlọpaa.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọjọ́ àkọ́kọ́ tí Baba Ijesha bá ọmọ mi lòpọ̀ ní mo ti mọ̀ àmọ́ kò sí ẹ̀rí - Princess
- Ọlọ́pàá kò lè dá wa dúró, á ṣe ìwọ́de Yoruba Nation l‘Abeokuta lọ́la - Yoruba Nation Agitators
- Ọ̀fọ̀ ńlá ṣẹ̀, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ èèyàn tẹ ara wọ́n pa, ariwo ẹkún sọ
- Saidi Balogun figbe ta pé wọn ń ba òun lórúkọ jẹ́ lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Iyabo Ojo gbé fídíò jáde nípa bí ọwọ́ ṣe tẹ Baba Ijesha
- Yekeen Ajileye, ọ̀gá mi nínú iṣẹ́ tíátà ṣẹ̀ mí, ó ṣẹ ẹlẹ́dàá mi - Abija
- Ìwọ́de alágbára ń bọ̀ l‘Eko láàrọ́ òní láti tako béèlì Baba Ijesha
- Ta ló gbé fọ́tò Aishal Lawal síta pé ó kú lọ́jọ́ ìkúnlẹ̀?
- Ọwọ́ ṣìnkún Àmọ̀tẹ́kùn tẹ afurasí agbẹ́bọn darandaran mọ́kànlá l‘Oyo
- Mò ń ké tantan, tí Buhari kò bá fí ipò sílẹ̀, ìbò 2023 kò ní wáyé - Father Mbaka
- Olórùka ti gba òrùka, n kò sí lórí àtẹ mọ́, ẹ má sanwó láti fẹ́ mi - Oluwo figbeta
"Ẹsun akọkọ ni pe o ba ọmọ kekere lopọ lasiko ti ko tọ ati nibi ti ko tọ, ẹẹkeji nipe o n fi ọwọ kan ọmọde naa laigba asẹ lọwọ awọn obi rẹ.
A ri wipe nipa ẹsun keji yẹn, gbogbo iwadi ti a ṣe lo ti fi idi ẹ mulẹ wipe, o sẹ si ẹsun ti wọn fi kan sugbọn à ń duro ki ile ẹjọ sísẹ, ka le gbe lọ si ile ẹjọ.

Ẹsun nina ọwọ ere oge si ọmọde ta mọ si Sexual Assault ni wọn le fun afurasi ẹsun naa ni beeli amọ ẹsun ifipa ba ọmọde lopọ, eyiun Defilement ni wọn kii gba oniduro rẹ fun afurasi nipinlẹ Eko."
Kọmisana ọlọpaa ni Eko fikun pe, Ile ẹjọ nikan lo le fi idi rẹ mu lẹ pe lootọ ni Baba Ijesha jẹbi tabi bẹẹ kọ, amọ isẹ tiwa ni ka se iwadii, ka si fi oju afurasi naa ba ile ẹjọ.
"A ti ri ẹri to dani loju wipe Baba Ijesha ṣe nkan to yẹ ko ṣe labẹ ofin sugbon a kò ti fi silẹ.
À ti gbe iwe ẹjọ rẹ (Case file) lọ si ileeṣẹ ijọba to wa nipa ọrọ ofin (Justice ministry) lati ba wa fi oju ofin woo.

Nkan ti àwọn ọlọpaa ń duro de niyẹn, esi ti wọn ba fun wa labẹ ofin ni yoo ṣokunfa igbesẹ ọlọpaa sugbọn esikesi ti wọn ba fun wa, ọlọpaa yoo jẹki àwọn araalu mọ.
Emi gẹgẹ bi ẹnikan bi Ọga ọlọpaa ipinlẹ Eko, n ko ti ni kiwọn fi silẹ o, o si wa ni ahamọ ti wọn fi si"
Ọga ọlọpaa tun sọ wipe, ẹsun ti wọn le gba iduro eeyan ni ẹsun ti Baba Ijesha sẹ sugbọn ti wọn ba gba iduro afurasi lori rẹ, ko tumọ si wipe ẹsun ti wọn fi kan ti pari tabi pe o ti jare ẹsun ti wọn fi kan.
"Ofin keji tun ni wipe afurasi ti wọn gba iduro rẹ lori iru ẹsun yii, ṣe eyi ko ni koba iwadi ti ọlọpaa ń se lọ, ti o ba jasi wipe yoo sakoba fun iwadi naa, agbara wa labẹ ofin lati mase gba iduro ẹni bẹẹ."

Odumosu wa mọ riri awọn ajafẹtọ ẹni to n se iwọde naa fun ọgbọn agba ti wọn lo lasiko iwọde wọn, to si ni ahesọ ọrọ ni pe wọn fẹ fun Baba Ijesha ni beeli.
"Ko si ẹni to n dunkooko mọ wa lati tu Baba Ijesha silẹ, bẹẹ ni ko si ẹni to n wa eekanna mọ mi lọrun bii Kọmisana ọlọpaa.
N ko le se ohun ti n ko ni awijare fun labẹ ofin, emi funra ara mi si ni mo n se amojuto gbogbo ẹsun to ba jẹ mọ iwa iyajusini laarin takọ-tabo".

Iwọde alagbara n bọ l‘Eko laarọ oni lati tako beeli Baba Ijesha
Saaju la ti sọ fun yin pe, iroyin to n tẹ wa lọwọ bayii ti salaye pe iwọde alagbara kan yoo waye ni aarọ oni ọjọ Ẹti nilu Eko, lati ta ko gbigba beeli Baba Ijesha.
Baba Ijesha ni gbajumọ osere tiata ti wọn fẹsun kan pe o nawọ ere oge si ọmọde ọmọ ọdun mẹrinla kan laipẹ yii, to si wa ni ahamọ ọlọpaa ni agbegbe Panti nilu Eko.
Afurasi yii ni iroyin kan sọ pe wọn yoo gba beeli rẹ, ti yoo si maa lọ sile lati maa lọ koju ileẹjọ to ba ya, ti ahesọ iroyin kan si ni, fidio fìdí rẹ múlẹ pe lootọọ ni Baba Ijesha ba ọmọdebinrin naa ni ajọṣepọ tipa tipa.
- Ẹ̀yin tẹ tako béèlì Baba Ijesha, ẹ̀ ń palá sẹ́nu ni - Yomi Fabiyi
- Iyabo Ojo gbé fídíò jáde nípa bí ọwọ́ ṣe tẹ Baba Ijesha
- Ẹ̀yin tí Baba Ijesha bá ọmọ tàbí àbúrò yín lòpọ̀ láìtọ́, ẹ fi ẹjọ́ ṣùn mí - Princess Comedian
- Iyabo Ojo àti Foluke Daramola tako ara wọn lórí ọ̀rọ̀ Baba Ijesha
- Ẹgbẹ́ òṣèré tíátà TAMPAN sọ̀rọ̀ sókè lórí ẹ̀ṣùn bíbá ọmọdé lòpọ̀ tí wọn fi kan Baba Ijesha
- Gbogbo abiyamọ aye ẹ gba wá, wọ́n ti fẹ́ tú Baba Ijesha silẹ - Iyabo Ojo figbe ta
- Òṣèré tíátà gbọnmú lórí ẹnu àbùkù tó ń kun àwọn òṣèré Yorùbá torí Baba Ijesha
- Ipa tí Fathia Balogun kó nínú bí mo ṣe dèèyàn lágbo òṣèré fíìmù Yorùba rèé - Baba Ijesha
Amọ iroyin to n tẹ wa lọwọ bayii ti salaye pe awọn ẹgbẹ ajafẹtọ ọmọniyan lorisirisi ati awọn obinrin to jẹ abiyamọ ti n gbaradi lati tako igbesẹ gbigba beeli Baba Ijesha naa.
Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ lori iwọ̀de alagbara to n bọ naa, agbẹjọro ati ajafẹtọ awọn obinrin, Oluwatoyin Ojo sọ pe ileeṣẹ ọlọpaa ni oun ko le sọ pe awọn ko le fidi rẹ mulẹ pe Baba Ijesha jẹbi ẹsun ti wọn fi kan an.

Oríṣun àwòrán, @d_lowla
Ajafẹtọ ẹni naa ṣalaye pe ọmọdebinrin yii sọ pe Baba Ijesha ba oun lajọṣepọ nigba toun wa ni ọmọ ọdun meje, pẹlu afikun pe Baba Ijesha tun ki kọkọrọ bọ oun loju ara.
Bakanna ni Baba Ijesha fun ra rẹ jẹwọ pe lootọọ loun fipa ba ọmọdebinrin yii to n gbe lọdọ adẹrinpoṣonu, Princess lọpọ.
"Lẹyin ti ẹrọ CCTV tu aṣiri bi Baba Ijesha tun ṣe fipa ba ọmọ naa ni ajọṣepọ tàn nígbà to pe ọmọ ọdun mẹrinla, n ṣe lo n bẹbẹ fún aforiji pe iṣẹ Esu ni.
Ati pe ile iwosan fidi rẹ mulẹ pe, ẹnikan ti fipa ba ọmọde naa lopọ lẹyin ayẹwo ti wọn ṣe fún ọmọ ọhun.
Ko gba ibi kan ye mi ohun to mu kawọn ọlọpaa sọ pe ko si ẹri to daju pe lootọọ ni Baba Ijesha fipa ba ọmọ naa lopọ," ajafẹtọ awọn obinrin ṣalaye.
Agbẹjọro naa sọ pe idi ni yii toun at'awọn ọmọ Naijiria kan fi fẹ ṣe iwọde lọ sọdọ awọn ọlọpaa lori ọrọ naa ni aarọ ọjọ Ẹti.
Ajafẹtọ awọn obinrin yii ko ṣai mẹnu ba ipa ti iyanṣẹlodi awọn oṣiṣẹ eto idajọ le ni lori ọrọ naa .
O ni lootọọ ni eeyan ko gbọdọ lo ju ọjọ kan lọ ni atimọle, ti wọn ba fi ẹsun ti wọn le gba beeli rẹ kan an.
Agbẹjọro naa ṣalaye pe eeyan ko gbọdọ lo ju ọjọ meji ni atimọle lọ ti ileẹjọ ba jina labẹ ofin orile-ede Naijiria.
O ṣalaye pe ileẹjọ lo le sọ bo ya Baba Ijesha jẹbi ẹsun ti wọn fi kan an tabi ko jẹbi.
O ni ti tawọn ọlọpaa ni lati gbe ẹsun ti wọn ba mu wa fún wọn lọ sí ilé ẹjọ.
Bẹẹ ba gbagbe, ọpọ awọn obinrin to jẹ osere tiata ati iya ọmọ ti ọrọ kan, Princess ni wọn se iwọde kan l‘Ọjọbọ ni agọ ọlọpaa Panti, lati tako gbigba beeli baba Ijesha.




















