Eniola Badmus: Ẹ má se ọ̀fọ̀ mi, alaàyè ní mí, ń kò kú - Eniola Badmus

Oríṣun àwòrán, eniola_badmus
Gbajumọ osere tiata, Eniola Badmus ti kede pe kawọn eeyan ye sọkun oun nitori alaye ni oun, oun ko tii ku rara.
Eniola, to fi fidio soju opo Instagram rẹ wa sọ fawọn ololufẹ rẹ, ẹbi ara ati ọrẹ pe ko ko ko ni ara oun le .
Lalẹ ọjọ Isẹgun ni iroyin kan n ja kiri ori ayelujara pe Eniola Badmus wa lara awọn eeyan tawọn sọja yinbọn mọ ni agbegbe Lekki lati pinwọ iwọde EndSARS to n waye nibẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọjọ́ Ìsẹ́gun di ọjọ́ ìbànújẹ́ fún ọ̀pọ̀ ìdílé ní Nàíjíríà torí òkú tó ṣùn
- Ọ̀dọ́ 30 ń gba ìtọ́jú lọ́wọ́ nílé ìwòsàn torí ọ̀gbẹ́ ìbọn ní Lekki - Sanwo-Olu ṣàlàyé
- Àwọn ṣọ́jà ṣíná ìbọn bolẹ̀ ni Lekki Tollgate
- Àwọn ọlọ́dẹ darapọ̀ mọ́ ìwọ́de #EndSARS l'Osogbo, wọ́n ní kò sáyè fún jàǹdùkú mọ́
- Kíní ìtumọ̀ ''Sọ̀rọ̀ Sókè'' tí àwọn afẹ̀họ́núhàn EndSars ń lò káàkiri
- Ìpínlẹ̀ Ogun náà ti ilé ìwé títí dí ọjọ́ Ajé tó m bọ̀, kò ní sí lílọ bíbọ̀ ọ̀kádà fún wákàtí 24
- Buhari, jáde bá ọmọ Nàíjíríà sọ̀rọ̀, orí àgbá ẹ̀tù la dúró lé - NUJ pariwo
Amọ Eniola se fidio naa sita lati fi ọkan awọn ololufẹ rẹ naa balẹ pe ibọn ko ba oun.

Oríṣun àwòrán, eniola_badmus
Eniola ni " Mo wa laye, bẹẹ ni mo wa laaye, ko ko ko ni ara ọta mi le. Mo si dupẹ lọwọ gbogbo ẹyin tẹ kan si mi .
Ara mi ya, ko si si ohun to se mi, koda n ko jade sita lonii.
N ko jade kuro nile ni ana, n ko si nile iwosan.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
O fikun pe oun fi aago ipe oun silẹ nile lasiko ti oun rin lọ fun ere idaraya, nigba ti oun de ni oun ri pe awọn eeyan ọọdunrun ti pe oun.
O ni ẹnu ya oun pupọ, to si n dupẹ pe wọn ku ifẹ oun.












