Ogun Accident: FRSC ní Sokoto làwọn èrò náà ti ń bọ̀ wá sí Ijẹbú Ode

Oríṣun àwòrán, Abiodun
Iroyin to n tẹ wa lọwọ fi ye ni pe ọpọ oku lo ti sun, ti ọkẹ aimọye si farapa lasiko ti ọks akẹru kan rebọ sinu odo Ogun lopopona Ibadan silu Ijẹbu Ode lọjọ Isẹgun.
Iroyin naa ni ọkọ akẹru ọhun, ti nọnba rẹ jẹ XE331MKA lo ko ero bii mejidinlọgọta, to si n bọ lati ilu Sokoto wa si Ijẹbu Ode lasiko to rebọ sinu odo Ogun ni idaji kutu hai ana.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọ̀gọ́rún sọ́ọ̀bù, àìmọye dúkìá ni iná tún jó lọ́jà Sabo nílùú Sagamu
- Malami, IGP àti alága APC Oyo ni yóò káwọ pọ̀'yìn rojọ nítori àwọn alaga Kansu tẹlẹri
- Ẹ ta kété sí àjọṣepọ̀ tí kò bá fún yín láyọ̀ torí ẹ̀mí kò ní ààrọ̀ - Àwọn òṣèré tíátà gbarata lórí ìdájọ́ ikú
- Ojora ń mú mi lọ́wọ́ lórí ìkọlù tó wáyé, ara mi kò tíì balẹ̀ - Toyosi Adesanya
Gẹgẹ bi oludari fun ajọ ẹsọ oju popo, FRSC, ẹka tipinlẹ Ogun, Clement Oladele yi sọ fun awọn akọroyin, o seese ko jẹ pe o ti rẹ awọn arinrinajo naa dẹnu lo mu ki ijamba naa waye.

Oríṣun àwòrán, Others
"Ni kete ti isẹlẹ yii to wa leti, lawọn osisẹ wa lati ẹka ti Ijẹbu Ode ati Ago Iwoye, yara lọ sibi ti isẹlẹ ọhun ti waye, ti wọn si ko awọn oku to fori sọta ijamba naa lọ sile igbokusi, nigba tawọn to farapa wa ni ile iwosan ijọba nilu Ijẹbu Ode."
Oladele wa rọ awọn ero lati maa rinrinajo pẹlu ọkọ ti wọn se fun ẹru kiko nikan nitori awọn ijoko wọn ko wa fun ijoko.









