Busola Dakolo: Ẹ̀sùn tí mo fi kan pásítọ̀ ìjọ COZA ṣì dúró digbí

Oríṣun àwòrán, Busola dakolo
Busola Dakolo sọ fun BBC lọsan Ọjọru pe oun ko tọwọ bọ iwe kankan to tako ẹsun ifipabanilopọ to fi kan Pasitọ agba ijọ Commonwealth of Zian Assembly, Biodun Fatoyinbo.
Ṣaaju ni iwe iroyin UK Guardian fi iroyin sita pe awọn fi ọrọ wa Busola lẹnu wo, o si sọ fun awọn pe awọn ọlọpaa to di ihamọra nkan ijagun fi ipa mu oun tibọn-tibọn lati fi ọwọ si iwe kan ti wọn kọ oriṣiriṣi nkan to le jẹ ẹri pe irọ ni gbogbo ẹsun to fi kan Fatoyinbo si.
Iwe iroyin UK Guardian jabọ pe Dakolo ṣalaye pe ọlọpaa kan gbe ibọn dani, ti ikeji si ni ki oun tọwọ bọ iwe ti wọn lo wa lati ọdọ ọga agba ọlọpaa.
''Ọkan ninu wọn mu ibọn dani ti mo si ri wi pe ẹni keji mu iwe kan lọwọ. Wọn sọ fun mi pe lati ọdọ ọga agba ọlọpaa ni Abuja lawọn ti wa, ti wọn si ni mo ni lati buwọ lu iwe tawọn mu wa.''
Nile Busola Dakolo ati ọkọ rẹ Timi nilu Eko ni wọn ni iṣẹlẹ yi ti waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Mo fẹ́ pa ara mi torí ojú àbùkù tí wọn ń fi wò mí pé mo fi iṣẹ́ abẹ bímọ"
- Fulani kò leè dúró, táa bá lo ohun ta jogún lọ́dọ̀ àwọn bàbá wa - Sunday Igboho
- Ọjà Àgbáláta ní Badagry rèé, níbití ẹran ejò ti dùn ju ẹran adìẹ lọ
- Ọlọ́run yóò ṣe ìdájọ́ nkan tó wà láàrin èmi àti Ireti Ajanaku - Tope Alabi
- A kò jáde ṣe ìwọ́de ìtagbangba mọ́, inú ọkàn wa lá ti máa ṣe ìfẹ̀hónú hàn - Revolution Now
Arabinrin Dakolo sọ pe ọsẹ bi i meji sẹyin ni oun ṣe ifọrọwanilẹnuwo naa pẹlu UK Guardian.
O fi idi rẹ mulẹ lori Instagram pe irọ ni iroyin to n lọ kaakiri igboro pe oun fi ọwọ si iwe naa. O sọ pe ẹjọ ti oun pe sọdọ awọn ọlọpaa ṣi n tẹsiwaju.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post








