Sylvester Oromoni death: Kókó mẹwàá nínú òfin ìpínlẹ̀ Eko lórí ẹgbẹ́ òkùnkùn rèé

Ipinle Eko

Oríṣun àwòrán, @Lagos

Oriṣiiriṣii nkan l'awọn eeyan ti n sọ nipa bi ẹgbẹ okunkun ṣe n gbilẹ sii to fi de ile ẹkọ girama bayii, lẹyin iku akẹkọọ ile ẹkọ Dowen, Sylvester Oromoni niluu Eko.

Ọpọ lo ti kepe ijọba ipinlẹ Eko lati ṣe iwadii lori iku Oromoni lẹyin tawọn obi ọmọ naa sọ pe Sylvester darukọ awọn akẹkọọ kan wí pe awọn lo lu oun lalubami ki ẹlẹmi to gbaa.

Ẹwẹ, ile igbimọ aṣofin ipinlẹ Eko ti ṣe agbekalẹ ofin to tako ẹgbẹ okunkun loṣu keji ọdun 2021 eleyii ti Gomina Babajide Sanwo-Olu buwọ lu.

Wọnyi ni koko mẹwaa to wa ninu ofin to tako ẹgbẹ okunkun nipinlẹ Eko:

1. Ẹwọn ọdun mọkanlelogun ni ijiya fun ẹnikẹni to ba jẹ ọmọ ẹgbẹ okunkun tabi ti a ba n pe eeyan lati darapọ mọ ẹgbẹ okunkun nipinlẹ Eko.

2. Ẹwọn ọdun mẹẹdogun ni ijiya fun ẹnikẹni ti o ba da ẹgbẹ okunkun silẹ tabi ẹni to ba gba ki wọn ṣe ipade ẹlẹgbẹ okunkun ni ile rẹ.

Àkọlé fídíò, Mama Deeper Life Ondo

3. Ẹnikẹni to ba fẹ fi ipa mu eeyan wọ inu ẹgbẹ okunkun yoo fi ẹwọn ọdun mẹẹdogun tabi meedogbọn jura.

4. Ẹlẹgbẹ okunkun ni ẹnikẹni ti wọn ba ti wọn ba ri ami tabi akọsilẹ ẹgbẹ okunkun pẹlu rẹ.

Àkọlé fídíò, Ìdí tí Tòmátò ẹ̀sà kò ṣe dára fún ìlera yín; wo àwọn kókó márùn-ún yìí

5. Ẹwọn ọdun mẹẹdogun ni ijiya fun ẹlẹgbẹ okunkun ti wọn ba ka ibọn mọ lọwọ ti o si n gbiyanju lati fi ipa mu elomiran wọ inu ẹgbẹ okunkun.

6. Ẹwọn ọdun mọkanlelogun n duro de ẹlẹgbẹ okunkun to ba dana sun eeyan tabi dukia ẹnikẹni tabi da kẹmika asiidi si eeyan lara.

Àkọlé fídíò, Murphy Afolabi: Kò dùn mí tí wọn bá ṣe yẹ̀yẹ́ mi torí mò fi sí pe ṣí, èdè Osogbo ìlú mi ni

7. Ẹwọn ọdun mọkanlelogun ni ijiya fun ẹlẹgbẹ okunkun to ba bẹ ẹgbẹ rẹ lọwẹ lati gbẹsan tabi ṣe ijamba fun ẹnikẹni nipinlẹ Eko.

8. Akẹkọọ laṣẹ lati darapọ mọ ẹgbẹ to ba forukọ silẹ pẹlu awọn alaṣẹ ile ẹkọ rẹ nikan.

Àkọlé fídíò, Afeez Akintunde: Àwọn ẹbí Tula Oyo figbe tá pé kò ní ohunkohun ṣe pẹ̀lú Yoruba Nation

9. Akẹkọọ to ba darapọ mọ ẹgbẹ kẹgbẹ to lodi sofin yoo fi ẹwọn ọdun meji jura.

10. Ẹnikẹni to ba ṣe iranwọ tabi daabo bo ẹlẹgbẹ okunkun yoo fi ẹwọn ọdun mẹẹdogun jura.

Àkọlé fídíò, Àwọn òṣìṣẹ́ Adedoyin jẹ́wọ́ fún wa pé àwọn pa àbúrò mi, ọ̀gá Adedoyin sì mọ̀ síi - Ẹ̀gbọ́n Timothy Adegoke