End SARS protest: Àwọn olùwọ́de EndSARS bíi mẹ́sàn án ló ṣì wà ní àhámọ́ lẹ́yìn oṣù mẹ́jọ - Ajàfẹ́tọ́

Oríṣun àwòrán, Omoyele Sowore
Awọn ẹgbẹ ajafẹtọ ọmọniyan kan ti ke si ijọba lati tu awọn eeyan to wa ni ahamọ silẹ lẹyin iwọde EndSARS to waye lọdun 2020.
Gẹgẹ bii ohun ti a gbọ ko din ni eeyan mẹsan an to ṣi wa ni ahamọ ni ipinlẹ Ondo, Ekiti, Eko ati ilu Abuja.
Lara awọn eeyan naa ni Kemisola Ogunniyi to ṣẹṣẹ bi ọmọ tuntun jojolo ninu ọgba ẹwọn to wa lagbegbe Surulere niluu Ondo, iyẹn ni ipinlẹ Ondo.
Oludije sipo Aarẹ labẹ asia ẹgbẹ oṣelu AAC lọdun 2019, Omoyele Sowore pin aworan Kemisola loju opo ayelujara rẹ, o ni ilu Akure ni wọn ti fi panpẹ ofin mu ọmọdebinrin naa nitori o farajọ ọkan lara awọn to dana sun ọọfisi ẹgbẹ APC to wa niluu naa.
Nigba ti BBC Yoruba kan si agbẹjọro Kemisola, Tope Tomekun, o sọ pe awọn ti n gbe igbesẹ lati yọọ ninu igbekun to wa lati nnkan bii oṣu mẹsan sẹyin.

Oríṣun àwòrán, Omoyele Sowore
O ni "Lọwọlọwọ bi a ṣe n sọrọ yii, mo ti n kọwe ẹsun si gomina ipinlẹ Ondo, Rotimi Akeredolo, ati agbẹjọro agba, to fi mọ adajọ agba ipinlẹ Ondo lori ọrọ naa."
BBC Yoruba tun kan si ọkan lara awọn ajafẹtọ to n da si ọrọ ọhun, Netufo Tomide, o sọ pe kii ṣe iya kekere lo jẹ Kemisola ninu ahamọ to wa.
O ni "Wọn mu Kemisola pẹlu awọn eeyan miran lẹyin ti wọn fẹsun kan wọn pe awọn lo dana sun ọọfisi ẹgbẹ oṣelu APC lasiko ifẹhonuhan EndSARS lọdun 2020."
O ṣalaye pe lara awọn to ṣi wa ni ahamọ ni ọmọ ọdun mọkanlelogun ti orukọ rẹ n jẹ Samuel Ojo ati Ayodele Ibukun, eyii to ni oyun oṣu meji bajẹ mọ lara lasiko ti awọn ọmọ ogun n fiya jẹ, koda o ni wọn ko tii fọ inu rẹ ti oyun ọhun bajẹ si titi di asioko ti a n ko iroyin yi jọ.

Oríṣun àwòrán, Kemisola Ogunniyi
O pari ọrọ rẹ pe gbogbo akitiyan awọn lati yọ Kemisola atawọn mii ni ahamọ ni ko tii so eso rere.
- Wo ikú tó pa Kenneth Kaunda, Ajìjàgbara fún òmìnira Áfíríkà tó gbẹ̀yìn
- Iyabo Ojo bẹ̀rẹ̀ ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ pẹ̀lú máníjà rẹ̀ tẹ́lẹ̀ lórí ẹ̀sùn olè jíjà
- Lẹ́yìn ọdún kan tí àwọn ènìyàn ìpínlẹ̀ Borno hó lé lórí, Ààrẹ Buhari ṣe àbẹ̀wò sí Borno
- Wo ikọ̀ aláàbò tuntun tí yóò gba iṣẹ́ ọlọ́pàá SARS ṣe l'Eko
- Àwọn agbébọn ti jí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ míì gbé lọ ní Kebbi
Lẹyin naa lo ke si ijọba lati fi oju ṣunukun wo ọrọ naa, ki alaiṣẹ ma baa jiya ẹṣẹ ti mọ ohunkohun nipa rẹ.
Oṣu kẹwaa ọdun 2020 ni iwọde EndSARS naa bẹrẹ ni irọwọrọsẹ, ṣugbọn nigba to di asiko kan, awọn janduku wọ aarin awọn oluwọde ọhun, ti wọn bẹrẹ si n da ilu ru.
Ọpọ ẹmi lo ba iṣẹlẹ naa lọ kaakiri Naijiria, to fi mọ awọn olufẹhonuhan atawọn agbofinro.
Bẹẹ naa ni ọpọ dukia sọnu, paapaa niluu Eko, Akure ati Benin.
- Gani Adams kọ lẹ́tà sí àjọ UN, AU, US lórí ààbò tó mẹ́hẹ àti ìpànìyàn darandaran
- Ṣé Princess lè sọ fáráyé iye ìgbà tó ti bọ́ aṣọ sí ìhòhò níwájú Baba Ijẹsha? -Mọlẹbi baba Ijẹsha gbarata
- Nǹkan tí a mọ̀ nípa ìlera Asiwaju Ahmed Tinubu
- Ayédèrú òṣìṣẹ́ ìjọba ni Baba Ijesha fà kalẹ́ ló jẹ́ kó ṣì wà láhámọ́ - Ọlọ́pàá
- Ojúbọ irúmọlẹ̀ tó jẹ́ ibùdó ìdìbò àti ìbùdó 740 ayédèrú míì gba ìwọ́gilé INEC















