Muhammadu Sanusi II: Mi ò ni ìpinu láti du ipò òṣèlú kankan ní Naijiria

Mi ò pinu láti du ipò òṣèlú kankan ní Naijiria - Muhammadu Sanusi II

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Emir ilu Kano tẹlẹ, to tun jẹ Alfa Agba ìjọ ẹlẹ́sìn Tijaniyya ni Naijiria, Muhammadu Sanusi, ti sọ pe oun ko ni erongba lati du ipo oṣelu ni Naijiria, àmọ́ o ni oun yoo tẹsiwaju lati ma a tọ araalu sọna lori oludije to yẹ.

Muhammadu Sanusi II, to sọ ọrọ naa nibi ipade akọkọ to ṣe pẹlu àwọn Muqaddimai ati Shaykhs ninu ìjọ ẹlẹ́sìn naa gẹgẹ bi Caliph wọn sọ pe awọn nkan ti oun n sọ ko tumọ si pe oun yoo ṣe oṣelu.

O ni "ti a ba ri awọn to ṣe e fi inu tan, to ba sọ pe awọn yoo ṣe dáadáa fun araalu, a gbọdọ parapọ̀ ṣe atilẹyin fun wọn".

Àkọlé fídíò, Baba Ijesha Rape Case: Yomi Fabiyi ní òun nìkàn lòun rí ara òun tó dúró tí Baba Ijesha

O ni ti araalu ko ba ṣe bẹ ẹ, o se e ṣe ko lewu fun Naijiria

O ni eto ẹ̀kọ́ fun awọn ọmọde ṣe pataki, ki awọn ìṣòro to n koju Naijiria to dopin.

O sọ pe laisi ẹ̀kọ́, ẹrú ni awọn ọmọ ẹ̀yà Ariwa Naijiria yoo maa ṣe fun awọn ẹ̀yà to kù.

Sugbọn, àwọn ẹnikan lara awọn alfa mii to tun sọrọ níbi eto naa, Sheikh Halliru Maraya, sọ pe yatọ si awọn imọran Sanusi, o ṣe pataki lati fi adura kun.

O sọ pe o jẹ dandan fún àwọn eeyan lati ni ibẹru Ọlọ́run, ki àwọn adari naa si daabo bo ẹ̀mí ati dukia awọn eniyan, ki wọn o si pese fun aini wọn.