Father Mbaka: Àwọn iléeṣẹ́ ńláńlá ló yẹ kí Buhari kọ́ dípò ríra ohun ìjà olóró

Oríṣun àwòrán, State House Abuja
Gbajugbaja oniwaasu nni, Fada Ejike Mbaka tun ti fi ikilọ ranṣẹ si aarẹ Buhari lori awọn ohun elo ija to n kojọ.
Mbaka lasiko to n waasu ninu ijọ rẹ, Adoration Ministry ni ilu Enugu ni, o ṣe ni laanu pe ohun ija ti aarẹ Buhari n kojọ yii gan an ni yoo rẹyin orilẹede NaijIria.
Ohun to gba aarẹ Buhari ni iyanju lati ṣe ni ki o kọ awọn ileeṣẹ nla nla ti yoo pese iṣẹ fun awọn eniyan.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kwara dá ọ̀gá ilé Keu tí wọ́n ti lu àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bí i bàrà dúró
- A kò da iṣẹ́ sílẹ̀ mọ́, ó di ọjọ́ míì, ọjọ́ re - IPMAN, PTD
- "Èmi ni mo sọ fáwọn ọ̀gá ilé Keu pé kí wọ́n lu ọmọ mi bí ẹran"
- Agbẹjọ́rò wọ́ ìjọba lọ sílé ẹjọ́ pé kó yọ kéú kúrò lára owó Náírà
- Buhari, ìwé òfin 1999 ni ìparun Naijiria, tètè fà á ya - Tunde Bakare
- Gómìnà Yoruba, ẹ dúró lé ìjọba àpapọ̀ lọ́rùn pé kó fi Sunday Igboho sílẹ̀ - Gani Adams
- Ìjọba ìpínlẹ̀ Kwara dá ọ̀gá ilé Keu tí wọ́n ti lu àwọn akẹ́kọ̀ọ́ bí i bàrà dúró
- Ìdí rèé tí mo fi gbà kí ọkọ mi má a ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ìyá àti àbúrò mi
''Aarẹ Buhari ti o ko ba ṣọra, awọn ohun ija ọkọ baluu ofurufu to n ra wọnyii ni wọn yoo lo lati fi doju orilẹede Naijiria bolẹ.
''Ẹ jọwọ ẹni akọkọ to ba ri aarẹ Buhari lẹyin iwaasu yii ni ko jiṣẹ fun un lori ọna iparun to wa ninu kikọ awọn dukia ijagun pamọ.''
''Ọlọrun lo ni ki n sọ fun aarẹ Buhari bẹẹ ni asiko yii.''
''O to gẹ lori ọrọ rira ohun ija ijagun, kọ kọ kọ awọn ileeṣẹ nla nla.
Amọ ni ọsẹ to kọja lasiko ti aarẹ Buhari sọrọ lo ni pe awon ti n ko awon ohun ijagun tuntun miran wọ orilẹede Naijiria lati awọn orilẹede to fẹran wa.
Buhari ni awọn ohun ijagun naa ni wọn yoo fi koju eto aabo to dẹnukọlẹ kaakiri orilẹede Naijiria.
''Awọn ohun ija yii yoo ran wa lọwọ lati tete bori eto aabo to dẹnukọlẹ.''

"Ó ṣeéṣe ká ta gáàsì 12.5kg ní ₦10,000 kó tó di December ọdún yìí"

Ẹgbẹ awọn alagbata gaasi idana ti n kọminu lori bi wọn ko ṣe ri ọja ta, eyii to mu ki gaasi ọhun ma fi ojojumọ gbowo lori ni Naijiria.
Akọwe agba ẹgbẹ naa, Bassey Essien sọ nibi ipade ita gbangba kan ti ẹgbẹ naa ṣe pe o ṣeeṣe ki iye owo ti awọn araalu n ra gaasi naa di ẹgbẹrun mẹwaa ko ti do oṣu kejila ọdun yii.
Iwọn gaasi 12.5kg ti awọn eeyan n ra ni ẹgbẹrun mẹrin ibẹrẹ yii ti di nnkan bii ẹgbẹrun meje si mẹjọ bayii.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wo ìtàn ayé Sunday Igboho, gbajúmọ̀ ajìjàgbara fún ilẹ̀ Yorùbá
- Ilé Sunday Igboho ń gbàlejò ọ̀pọ̀ ọmọ Yorùbá tó fẹ́ sàmì ayẹyẹ ọjọ́ ìbí lẹ́yìn rẹ̀
- Ẹ múra o, ọ̀wọ́n gógó epo bẹntirolú bẹ̀rẹ̀ lọ́jọ́ Ajé nílẹ̀ Yorùbá
- Wo ewu tó wà fún ìyálamọ tó ń jẹ olúbi ọmọ lẹ́yìn ọjọ́ ìkúnlẹ̀
- Ìgbagbọ́ mi nínú Nàíjíríà kò yinjẹ, ìrètí mi nípa ọjọ́ ọ́la wa sì le koko - Obasanjo
- Buhari, fa iwé òfin ọdún 1999 ya, ko sì pe ìpàdé àpérò aráàlú - Yorùbá VOR
- Wàládè dé! Àwọn obìnrin aṣaralóge wọ gàù ikọ̀ Taliban ní Afghanistan
- Àwàdà lásán ní Adeleke ṣe nípa ọ̀rọ̀ bàálù, kò sí òótọ́ níbẹ̀ - Ooni Ife
Awọn alagbata gaasi naa ni pupọ awọn ọmọ Naijiria lo ti bẹrẹ si n lo eedu ati ina igi nitori ọwọngogo gaasi.
Essien ni ijọba apapọ gbọdọ ṣe atunyẹwo awọn owo ori to n gba lori awọn ọja ti wọn n ko wọ Naijiria lati ilẹ okeere ati iye owo ori VAT.
O ni bi bẹẹ kọ, o ṣeeṣe ki awọn maa ta iwọn gaasi 12.5kg ni ẹgbẹrun mẹwaa naira.
O ni "Lonii yii, iye owo gaasi ti di ₦7,500 si ₦8,000, ṣugbọn awọn n gbiyanju ki owo naa ma baa wọn ju bẹẹ lọ."
"Fun apẹrẹ, iye ti a n ra ogun tọọnu gaasi ko to miliọnu marun un naira lọdun to kọja, ṣugbọn bayii o ti le miliọnu mẹwaa naira."
"Niwọn igba ti a ko ba ri ọja ra, iye ti a n taa fun awọn araalu gbọdọ gbowo lori dandan ni."
Nigba to sọrọ lori bi awọn alagbata ko ṣe ta daadaa bii ti atẹyinwa, o ni pupọ ọmọ Naijiria lo ti pada si lilo epo kẹrosini, sawdust, igi idana ati bẹẹ bẹẹ lọ.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, ẹgbẹ naa ti n ba ijọba jiroro lori ọna abayọ si iṣoro ọwọngogo gaasi ọhun laarin awọn to n ko wọ Naijiria lati oke okun ati awọn alagbata.
Ẹgbẹ naa pari ọrọ wọn pe yatọ si gaasi, silinda ti wọn rọ gaasi naa si tun ti gbowo lori ju ti tẹlẹ lọ nitori oke okun ni wọn ti n ko awọn eroja ti wọn fi n ṣe silinda ọhun wọ Naijria.



















