Tunde Bakare: Bí ọ̀pọ̀ ẹ̀yà ṣe ń lọgun láti kúrò ní Nàíjíríà fihàn pé a nílò àtúntò

Muhammadu Buari ati Tunde Bakare

Oríṣun àwòrán, Presidency

Adari ijọ ati pasitọ agba ijọ, Citadel Global Church, Pasitọ Tunde Bakare ti kesi Aarẹ Buhari lati fagile iwe ofin ọdun 1999 nitori ohun lo n ṣokunfa ifaṣẹyin fun Naijiria.

Bakare sọ eyi lasiko isin ni ile ijọsin rẹ to pe akori iwaasun ọhun ni ''Bi o ṣe n lọ lorilẹede Naijiria'', ''The state of the Nation''.

Isin naa waye ni gbagede ile ijọsin rẹ to wa ni olu ile ijọsin naa ni ipinlẹ Eko.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Pasitọ Bakare ni awọn idojuko to n ba orilẹede Naijiria finra ko ṣẹyin eto oṣelu to mẹhẹ lati ibẹrẹ wa, eleyii ti awọn ijọba ologun doju rẹ bolẹ nigba ti wọn gbakoso iṣejọba Naijiria.

Bakare ni ija ẹlẹyamẹya, ẹlẹsin mẹsin to fi mọ awọn ẹkun to n lọgun pe wọn fẹ kuro lorilẹede Naijiria, eleyii ti ko yọ ẹkun kankan silẹ, fihan pe Naijiria nilo atunto.

Àkọlé fídíò, Tunde Bakare: Àjọjẹ kò dún bẹ́nìkan kò ní ló fa ìjà S Igboho,bẹ́ẹ̀ ìjọbati gbẹ́rù kọjá orí

Gẹgẹ bi ọrọ rẹ, ohun to ṣe pataki kọ ni ibi ti aarẹ orilẹede yoo ti wa, to ba jẹ pe orilẹede Naijiria duro ire.

''O dami loju pe iwe ofin ọdun 1999 ko so eso rere kankan fun Naijiria, iku lo mu wa fun orilẹede yii.''

Bakan naa lo kesi aarẹ Buhari lati ṣe ojuṣe rẹ ki o si ye e gbe iṣẹ fun Ile Igbimọ Aṣofin ti Naijiria.

''Aarẹ Buhari, ya iwe ofin ọdun 1999 ko si ṣe atuntọ ati atunṣe orilẹede Naijiria pada.''

''Aibikita ni ki awọn kan ma a lọgun idibo gbogboogbo ọdun 2023 lai kọkọ wa wọrọkọ fi ṣe ada lori ọrọ atunto orilẹede Naijiria.

Àkọlé fídíò, Olota Of Ota: N kò fara mọ́ ìyapa Nàíjíríà, ìṣèjọba ẹlẹ́kùnjẹkùn ní ọ̀nà àbáyọ

Pasito Tunde Bakare wa kilọ fun aarẹ Buhari pe ti ko ba tun orilẹede Naijiria to, akọsilẹ yoo wa wi pe o kuna gẹgẹ bi aarẹ nigba to wa ni ipo.

Bakare to jẹ amofin ati agbẹjoro naa ti fi igba kan dije dupo igbakeji aarẹ pẹlu aarẹ Buhari ni idibo si ipo aarẹ ni ọdun 2011.

Amin iyasọtọ kan

Ìgbagbọ́ mi nínú Nàíjíríà kò yinjẹ, ìrètí mi nípa ọjọ́ ọ́la wa sì le koko - Obasanjo

Aarẹ Muhammadu Buhari ati Oloye Olusegun Obasanjo

Oríṣun àwòrán, The Presidency

Aarẹ tẹlẹ fun orilẹede Naijiria, Oloye Olusegun Obasanjo ti rọ awọn ọmọ Naijiria lati mase sọ ireti nu nipa orilẹede yii.

Obasanjo ni ẹpọn agbo kan n mi lasan ni, ko ni ja nitori awọn isoro to n ba Naijiria finra ko kuku ni gbe mi.

Oloye Obasanjo fi ọwọ idaniloju yii sọya lasiko to n sọrọ nibi eto kan to waye pẹlu ilẹ Amẹrika nile iyawe-kawe rẹ nilu Abeokuta.

Nigba to n sọrọ apilẹkọ nibi eto naa, Obasanjo ni mimi kankan ko mi igbagbọ ti oun ni nipa orilẹede yii pe ọjọ ọla yoo dara, ti ilẹ yii yoo si duro re.

Obasanjo, ẹni ti igbakeji alakoso ile iyawe-kawe rẹ, Kayode Aderinwale soju fun fikun pe isoro yowu ti kii ba maa koju Naijiria lọwọ kii se isoro ikọlu bikose isoro ipadasẹyin.

"Igbagbọ mi ninu Naijiria ko yinjẹ, ireti mi nipa ọjọ ọla si le koko, bi o tilẹ jẹ pe ọpọ lo n kọminu nipa baa se doola ọjọ ọla wa."

Àkọlé fídíò, Aremu: Eré ìtàn nípa ìbí, àti jéèyàn pẹ̀lú ìpèníjà Olusegun Aremu Obasanjo

"Mo ri ireti ninu ipinnu ọkan, itiraka ati iwa aikaibọnu awọn ọmọ Naijiria, mo si ri ireti ninu atako wọn nigba ti wọn ba sun wọn kan ogiri.

Mo ri ireti ninu ilakaka, ifọkansin ati igboya lasiko ti iyapa ba n koju wọn, mo si tun ri ireti nipa ọpọ ipinnu ọkan awọn ọdọ Naijiria lati se rere.

Mo tun ri ireti ninu bawọn ọdọ ati agbaagba ọmọ Naijiria se n fi gbogbo agbara wọn tako iwa ibi to n gbinlẹ lorilẹede yii.

Lakotan, mo tun ri ireti ninu ihuwasi ati igbesẹ awọn ọmọ Naijiria lati beere fun isejọba alagbada pẹlu ọgbọn atinuda wọn nipa orilẹede yii."

Olusegun Obasanjo ni ireti tun wa fun oun pe ọjọ ọla Naijiria yoo dara, ta ba wo iyapa ati ojulowo asa wa laarin iran ọmọniyan.

Àkọlé fídíò, Olusegun Obasanjo: Ọmú ìyá mi ti mo fi ń mùkọ ni kekere ló jẹ ki ń lókun