Monsurat Police Stray Shooting: Odumosu ṣé àbẹwò sí ìdílé Monsurat tí ọlọ́pàá yìnbon lú

Kọmisana ọlọpaa ni ipinlẹ Eko Hakeem Odumosu ti ṣe abẹwo si mọlẹbi arabinrin Monsurat Ojuade ti ibọn ba ni adugbo Ijeshatedo.
Ọrọ yi jẹyọ ninu atẹjade kan ti alukoro ọlọpaa Eko,Adekunle Ajisebutu fi sọwọ sawọn akọroyin.
O ni lasiko abẹwo rẹ, Kọmisana kọwọrin pẹlu awọn ọga agba ọlọpaa nipinlẹ naa ti wọn si ba mọlẹbi Monsurat kẹdun iku arabinrin naa.

Bẹẹ naa lo fi iwe ikẹdun jiṣẹ fun mọlẹbi to tun fi to wọn leti pe awọn ti mu ọlọpaa to yinbọn pa Monsurat,iyẹn Sajẹnti Samuel Philips.
O ni igbẹjọ labẹle n lọ lọwọ lori Philip.
Ni ọjọ Kọkanla oṣu Kẹsan ni aṣita ọta ibọn ba Monsurat.
Ọwọ́ tẹ ọlọ́pàá tó yìnbọn pa ọmọ ọdún 18 nílùú Eko
Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko ti sọ pe awọn ti fi ṣikun ofin mu ọkan lara awọn oṣiṣẹ rẹ to yinbọn pa ọmọ ọdun mejinlogun kan nipinlẹ Eko.
Agbẹnusọ ọlọpaa ipinlẹ Eko, CSP Adekunle Ajisebutu lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade to fi ṣọwọ si awọn akọroyin bo tilẹ jẹ pe o kọ lati fi orukọ tabi aworan afurasi naa lede.
- Okòòwò márùn ún tí o lè bẹ̀rẹ̀ nínú ilé rẹ̀
- Ìyàwó Wòlíì TB Joshua di olórí ìjọ Synagogue
- Ẹ dákun ẹ ran Iyabo Oko lọ́wọ́, ìyá ti ń ṣàárẹ̀ láti ọdún márùn ún sẹ́yìn, o ti kọjá agbára wa- Foluke Daramola Salako
- Ṣọ́ọ̀ṣì wó pa èèyàn méjì ní Taraba, àwọn míràn farapa
- Wo àwọn Fasiti Nàìjíríà tó gbégbá orókè lágbàyé
Atẹjade ọhun ni "O ti tẹ ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Eko leti pe aṣita ibọn ba ọmọ ọdun mejidinlogun kan, Monsurat Ojuade ni nnkan bii aago kan oru, ọjọ kọkanla, oṣu Kẹsan an, ọdun 2021, lasiko ti awọn ọtẹmuyẹ CID lọ ṣawari awọn adigunjale kan ni Ijeshatedo."
"Wọn gbiyanju lati doola ẹmi ọdọbinrin naa ṣugbọn o jade laye lasiko ti wọn n gbe lọ sile iwosan."
Ajiṣebutu tẹsiwaju pe kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Eko, Hakeem Odumosu ba ẹbi oloogbe naa kẹdun.
O fikun pe ọwọ awọn ti tẹ ọlọpaa to yinbọn pa ọmọ naa ati pe iwadii ti bẹrẹ, afurasi ọhun yoo si foju bale ẹjọ laipẹ lẹyin ti wọn ba ti kọkọ gba iṣẹ lọwọ rẹ.
Agbẹnusọ ọlọpaa naa ni eyii yoo jẹ arikọgbọn fun awọn ọlọpaa to ku ti wọn n ṣiṣẹ wọn bii ẹni ti ko ni ẹkọ to dantọ.
- Kí ló lè mú ẹni ọdún mẹ́tàlélógún tó wà ní ND2 yìí pokùnso?
- Ọmọ Naijiria tó ń ṣe Yahoo rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ̀rin he l'Amẹrika
- Ọ̀kan lára àwọn ọmọ Odunlade Adekola nídìí iṣẹ́ tíàtà sọ̀rọ̀ sókè lórí ẹ̀sùn pé ó ń bá àwọn lòpọ̀
- Ìwádìí ti tú àṣírí àwọn tó yìnbọn sí olùwọ́de EndSARS ní Tollgate l'Eko
- Wo ìdí tí àwọn obìnrin kan fi n yọ ilé ọmọ wọn kúrò
- Kí ló lè mú ẹni ọdún mẹ́tàlélógún tó wà ní ND2 yìí pokùnso?
- Wo díẹ̀ lára bí wọ́n ṣe sàmì ìrántì ìkọlù 9/11 ní America
Lẹyin naa lo ni bo tilẹ jẹ pe iṣẹlẹ naa jẹ eyii ti ko fun ileeṣẹ ọlọpaa lorukọ rere, awọn yoo tẹsiwaju lati maa dabo bo awọn araalu ati dukia wọn.
Ẹwẹ, lasiko ti ikọ BBC ṣabẹwo sile oloogbe naa lọjọ Aiku, inu ibanujẹ ọkan ni awọn mọlẹbi rẹ wa, ti wọn si n bere fun idajọ ododo lori iku aitọjọ to mu ọmọ wọn lọ.
- "Kò sí ìdáríjí fún àwọn jàndùkú mọ́ báyìí, a óò bẹ̀rẹ̀ sí ń ran wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Eledumare"
- Arákùnrin ẹni ọdún 28 kan tí bá omiyalé lọ ní Ibadan
- Ọ̀bẹ ti bá ọ̀gá DPO tó sọ ìbọn ọlọ́pàá nu lẹ́yìn tó gbé obìnrin sùn sí ọ́fíìsì rẹ̀ nídí
- Àwa ọmọ ìlú Igboho kò gbàbọ̀dè fún Sheikh Gumi o, gbọin-gbọin ni à wà lẹ́yìn Sunday Igboho
- Odunlade Adekola yarí lórí ìròyìn tó ní ó n bá àwọn obìnrin sùn kó tó fi wọ́n sínú fíímù rẹ̀
- Wo iye kọ́ńdọ́mù táwọn ọmọ Nàìjíríà fi ń ṣara rindin lọ́dún
- Ọmọ Naijiria tó ń ṣe Yahoo rí ẹ̀wọ̀n ọdún mẹ̀rin he l'Amẹrika














