Buhari Water Loan: Ilé aṣòfin ní òun ti fòǹtẹ̀ lu owóyàá ìpèsè omi fún ìgbà mẹ́ta láì sí ìyípadà

Oríṣun àwòrán, Unicef
Erongba Aarẹ Muhammadu Buhari lati ya ẹẹdẹgbẹrin miliọnu Dọla fun ipese omi, ti ba ijakulẹ pade niwaju Igbimọ Ile Aṣofin to n ṣagbeyẹwo gbese ti Naijiria .
Saaju ni Buhari ti kọwe si awọn aṣofin pe ki wọn o buwọlu ki oun ya owo naa, ki ijọba rẹ le ni anfaani lati pese omi fun awọn ọmọ Naijiria ni igboro ati igberiko lọdun 2022.
Eto naa ni wọn pe ni ''Sustainable Urban and Rural Water Supply, Sanitation and Hygiene (SURWASH),'' labẹ idari ileeṣẹ to n mojuto alumọni inu omi.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ọwọ́ ọlọ́pàá Cotonou tẹ akọ̀royìn tó fi fọ́nran ohùn Sunday Igboho síta
- Ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ lórí oyè ẹ̀sìn Grand Mufti Yorùbá tí Oluwo fi Mùsùlùmí kan jẹ
- Obìrin tó ń ta omi inú ọ̀rá subú pẹ̀lú ọmọ lẹ́yìn torí ebi
- Ẹ ṣì mí gbọ́ ni, a nílò ìrànwọ́ àwọn ìjọba ìpinlẹ̀ ní ọgbà ẹ̀wọ̀n - Aregbesola
- Wo orúkọ tuntun tí Facebook yóò má jẹ́ láti àkókò yíì lọ
- Wọ́n gbé ọmọ mi tó jẹ́ Babaláwo Sunday Igboho, a kò mọ ìrìn rẹ̀ láti oṣù mẹ́ta
- Ọkùnrin kan wọ gàù torí ọ̀rọ̀ tó fi ránṣẹ́ sí aya aláya lórí Whatsapp
- "Ẹlẹ́wọ̀n Abolongo pa méjì lára ọdẹ ìbílẹ̀ lásìkò tà ń ṣà wọ́n kiri ìgboro Oyo"
- Ìwà ìkà sí Yorùbá ni bí ìjọba ṣe ti bodè Seme láti 2019 - Gani Adams
Bi awọn aṣofin ṣe kọ ẹbẹ yii waye lẹyin wakati mẹrinlelogun ti awọn aṣofin kọ erongba ijọba lati yá igba miliọnu Dọla fi ra nẹẹti to n pa ẹfọn.
Ninu aba isuna ọdun 2022 ti Buhari gbe lọ sile aṣofin ni wọn kọ eyi si.
Awọn ọmọ igbimọ naa sọ pe ko bojumu lati tun ya owo lasiko ti Naijiria ni ọpọlọpọ gbese to n san lọwọ.
Alaga igbimọ naa, Sẹnetọ Clifford Ordia sọ pe igba mẹta ọtọọtọ ni wọn ti buwọlu owo yiya fun ipese omi.
Ordia sọ pe gbese ọtalenirinwo din mẹwa miliọnu Dọla kan wa nilẹ, bakan naa tun ni miliọnu mẹfa Dọla miran, ti wọn gba lọwọ Banki idagbasoke ilẹ Africa.
Wọn ni ileeṣẹ ijọba to n mojuto alumọni inu omi gbọdọ ṣalaye nkan to fẹ ẹ fi ẹẹdẹgbẹrin miliọnu Dọla ṣe fun ipese omi.
Ọkan lara awọn aṣofin naa, Obinna Ogba sọ pe awọn ọmọ Naijiria ko gbadun omi laduru owo ti wọn ti ya tẹlẹ.
Awọn ọmọ igbimọ naa fẹnuko lati ranṣẹ pe minisita fun ileeṣẹ ijọba naa, Adamu Suleiman pe ko wa a ṣalaye nkan ti wọn fi awọn owo ti wọn ya tẹlẹ ṣe.

















