Oyo Jailbreak: Aregbesola ní òun kò kọ̀ ìrànwọ́ CCTV tí Makinde fẹ́ rì sí ọgbà ẹ̀wọ̀n Abolongo

Oríṣun àwòrán, Rauf Aregbesola
Minisita fun ọrọ abẹle Ọgbẹni Rauf Aregbesola ti salaye pe oun ko kọ iranwọ ti gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde fẹ se si ọgba ẹwọn Abolongo nilu Oyo.
Aregbesola ni wọn si oun gbọ lori ọrọ naa ni eyi ti wọn ni oun sọ nigba ti oun n kopa lori eto redio kan nilu Ibadan lati ori foonu.
Atẹjade kan ti akọwe feto iroyin rẹ, Sola Fasure fisita lo sisọ loju ọrọ yii pẹlu afikun pe awọn ọbayejẹ ẹda kan lo n gbe iroyin ẹlẹjẹ naa kiri nitori ifẹkufẹ ara wọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Obìrin tó ń ta omi inú ọ̀rá subú pẹ̀lú ọmọ lẹ́yìn torí ebi
- Ẹ ṣì mí gbọ́ ni, a nílò ìrànwọ́ àwọn ìjọba ìpinlẹ̀ ní ọgbà ẹ̀wọ̀n - Aregbesola
- Wo orúkọ tuntun tí Facebook yóò má jẹ́ láti àkókò yíì lọ
- Wọ́n gbé ọmọ mi tó jẹ́ Babaláwo Sunday Igboho, a kò mọ ìrìn rẹ̀ láti oṣù mẹ́ta
- Ọkùnrin kan wọ gàù torí ọ̀rọ̀ tó fi ránṣẹ́ sí aya aláya lórí Whatsapp
- "Ẹlẹ́wọ̀n Abolongo pa méjì lára ọdẹ ìbílẹ̀ lásìkò tà ń ṣà wọ́n kiri ìgboro Oyo"
- Ìwà ìkà sí Yorùbá ni bí ìjọba ṣe ti bodè Seme láti 2019 - Gani Adams
"Saaju ni mo ti kọkọ rọ awọn ijọba ipinlẹ lati kọ awọn ile fun awọn afurasi tile ẹjọ ko tii se idajọ wọn nitori ida aadọrin awọn eeyan to wa lọgba ẹwọn lo n reti idajọ lọwọ.
Bakan naa ni mo sọ pe ijọba apapọ yoo mọ riri iranwọ tawọn ijọba ipinlẹ ba se lati sugba aayan to n lọ lọwọ nidi minu agbega bawọn ohun eelo amayedẹrun lawọn ọgba ẹwọn wa.
Amọ o se ni laanu pe awọn ọbayejẹ kan yi ohun ti mo sọ po lati gbe mi kọlu awọn araalu."
Aregbesola wa rọ awọn ijọba ipinlẹ atawọn eeyan ti ọrọ ilẹyii gberu lati ri daju pe agbega ba ilana eto idajọ nilẹ yii atawọn ohun elo to wa lawọn ọgba ẹwọn.

Seyi Makinde kò láṣẹ láti fi ẹ̀rọ CCTV sí ọgbà ẹ̀wọ̀n - Aregbesola

Oríṣun àwòrán, Seyi Makinde/Facebook
Minisita fun ọrọ abẹle lorilẹede Naijiria, Ogbeni Rauf Aregbesola ti ni Gomina ipinlẹ Oyo, Seyi Makinde ko ni aṣẹ lati fi ẹrọ camera CCTV si ọgba ẹwọn Abolongo ni ipinlẹ Oyo.
Eyi ko ṣẹyin ọrọ ti Gomina Makinde sọ lasiko to ṣe abẹwo si ọgba ẹwọn Abolongo, ti awọn agbebọn ṣekọlu si nipinlẹ naa lọjọ Ẹti.
O kere tan ẹẹdẹgbẹta awọn to wa ni ẹwọn ni wọn sakuro lọgba ẹwọn naa lasiko ti iṣẹlẹ ọhun waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wọ́n gbé ọmọ mi tó jẹ́ Babaláwo Sunday Igboho, a kò mọ ìrìn rẹ̀ láti oṣù mẹ́ta
- Ọkùnrin kan wọ gàù torí ọ̀rọ̀ tó fi ránṣẹ́ sí aya aláya lórí Whatsapp
- "Ẹlẹ́wọ̀n Abolongo pa méjì lára ọdẹ ìbílẹ̀ lásìkò tà ń ṣà wọ́n kiri ìgboro Oyo"
- Ṣé lóòtọ́ ni CBN n pín àádọ́ta bílíọnù eNaira lọ́ọ̀fẹ́ fún aráàlú?
- "Àwa ológun fipá gbàjọba ní Sudan láti dènà ogun abẹ́lé ni"
- Ìwà ìkà sí Yorùbá ni bí ìjọba ṣe ti bodè Seme láti 2019 - Gani Adams
- Ọmọ onílẹ̀ mẹ́ta kó sí páńpẹ́ ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn
- Wo ohun tí Yinka Alaseyori sọ nipa Tope Alabi ní àyájọ̀ ọjọ́ ìbí rẹ̀
- Ọmọ onílẹ̀ mẹ́ta kó sí páńpẹ́ ọlọ́pàá lórí ẹ̀sùn ìpànìyàn
Makinde lasiko to ṣabẹwo si ọgba ẹwọn naa ni ijọba oun yoo gbe igbesẹ lati ri pe eto aabo ko mẹhẹ ni awọn ọgba ẹwọn nipinlẹ Oyo.
O ni ijọba yoo pese awọn ohun eelo igbalode fun eto aabo bii CCTV, ki wọn le ma a tọpasẹ iṣẹlẹ to n waye nibẹ.
Amọ, lasiko to n fesi, olubadamọran lori ọrọ iroyin fun Aregbesola, Sola Fasure ni bi o tilẹ ṣe pe inu ire ni gomina Makinde fi sọ ọrọ naa, amọ ko laṣẹ tabi agbara lati ṣe iru nkan to jọ bẹẹ si awọn ọgba ẹwọn.
''Ohun ti Makinde le ṣe ni ki o gba awọn ni imọran nitori ileeṣẹ ijọba to n risi ọrọ abẹle, eleyii ti Aregbesola jẹ minisita rẹ, lo le e pa iru aṣẹ bẹẹ.''
''Bakan naa ni a ti n ṣiṣẹ lati mu idagbasoke ba awọn ọgba ẹwọn kaakiri orilẹede Naijiria, bẹrẹ lati ilu Abuja ati Kano.''
''O ṣe ni laanu pe iṣẹlẹ Abolongo waye ko to di pe atunṣe awọn ọgba ẹwọn de ipinlẹ Ọyọ.''
''Amọ iranwọ ti ijọba ipinlẹ le ṣe to wa ni ikawọ wọn ni lati ri pe awọn to wa ni ọgba ẹwọn ti wọn n duro de idajọ ri idajọ gba ni kiakia.''
''Sunkẹrẹ fakẹrẹ awọn adajọ lori awọn ẹjọ to wa ni ileẹjọ lo fa bi awọn ọgba ẹwọn yii ṣe kun fọfọ, ti ọpọlọpọ wọn si n reti idajọ.
O ni eyi lo fa afunpọ ni awọn ọgba ẹwọn yii, ti awọn agbebọn fi raye ṣekọlu si bẹ.''
''Ijọba apapọ ti bẹrẹ si ni kọ awọn ọgba ẹwọn to lee gba ẹgbẹrun mẹta eniyan lẹẹkan naa ni awọn ẹkun mẹfẹẹfa to wa lorilẹede Naijiria, ti eleyii to wa ni Abuja ati Kano pẹlu ileẹjọ wọn si ti wa ni ṣẹpẹ.''
''Ijọba ipinlẹ gbọdọ ran ijọba apapọ lọwọ lati ri pe awọn adajọ wọnyii n da ẹjọ lasiko lai si pe ki wọn ma a sun siwaju ni gbogbo igba, nitori agbara ti wọn ni ni ikawọ niyẹn kii ṣe ki wọn fi CCTV si ọgba ẹwọn.''
Amọ olubadamọran fun Aregbesola naa fikun un pe aba to dara ni gomina Makinde muwa, ti minista naa yoo si gbeyẹwo ni finifini.





















