Tope Alabi ṣe ọjọ́ ìbí, Adeyinka Alaseyori kọrin re kìí

Oríṣun àwòrán, Tope Alabi
Oniruru ọrọ ikinni lawọn eeyan ti bẹrẹ si n fi ṣọwọ si gbajugbaja olorin ẹmi, Tope Alabi lati sami si ayẹyẹ ọdun mọkanlelaadọta rẹ loke eepẹ.
Lara awọn eeyan jankan to n ṣe ayẹsi Tope Alabi ni Adeyinka Alaseyori to jẹ ki orin "Oniduro" di gbajumọ.
Alaseyori fi ikinni naa ranṣẹ si Tope Alabi loju opo Instagram ati Facebook rẹ.
- Iyabo Ojo tún sọ òkò ọ̀rọ̀ sáwọn òṣèré tíátà nínú fídíò tuntun tó gbé síta
- Ẹ wo àwọn gbajúmọ̀ ìlú tó sọ̀rọ̀ tako èrò Tope Alabi nípa orin "Oniduro Mi"
- Ẹ ṣeun, ẹ kú àdúrótì mi! Ẹ wo ọ̀rọ̀ tí Tope Alabi padà sọ nípa awuyewuye tó wáyé lóri orin Oniduro Mi
- O kú ogun àjàyé Tope Alabi, odò Jodani lo ṣẹ̀ṣẹ̀ là kọjà yìí o! Àmọ́ rántí pé ... - Mike Bamiloye
- Taní Wolí rẹ̀? Èmí ti jèrè ''Minister''; Woli Joshua Iginla fí ọkọ̀ ńla ta mí lọ́rẹ- Alaseyori tó kọ orin Oniduromi
- Yinka Alaṣeyori fi ọ̀rọ̀ ìjínlẹ̀ púpọ̀ àti omijé ṣàlàyé Oniduro Mi
- Wòlíì Genesis fèsì lórí ọ̀rọ̀ Tope Alabi nípa orin 'Oniduromi'
- Alaseyori kọ́ ló ni orin "Oniduro Mi", àmọ́ ìdí tí mi ò ṣe bá a jà pé ó jí orin mi kọ nìyìí - Tolu Adelegan
- Ẹ jọ̀wọ́ ẹ jẹ́ kí àláfíà jọba lórí orin "Oniduro Mi", ìyá ni Tope Alabi jẹ́ sí mi - Adeyinka Alaṣeyori
O ni "Ẹku ayẹyẹ ọjọ ibi yin o maami, ẹ ṣeun ti ẹ gba lati jẹ ohun ti Ọlọrun fẹ ki ẹ jẹ, ayọ yin ṣẹṣẹ bẹrẹ ni, ẹku oriire naa."
Ti ẹ ko ba gbagbe, ninu oṣu Kẹfa ọdun yii ni fidio kan gbode lori ayelujara, nibi ti Tope Alabi ti n bu ẹnu atẹ lu orin Oniduro, eyii to sọ Alaseyori di gbajumọ olorin ẹmi.
Ninu fidio ọhun ni Tope Alabi ti sọ pe Ọlọrun kii ṣe oniduro toun.
Tope Alabi sọ siwaju si ninu fidio naa pe ti eeyan ba kọ orin ẹmi, o yẹ ko maa gba imisi lati ọdọ ẹmi mimọ ko to gbe orin jade.
O fikun pe ti akọrin ba tun gba imisi lati ọdọ ẹmi mimọ naa tan, o yẹ ko maa fi ọgbọn ori gbe orin kalẹ.
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post
Ọrọ naa bi ọpọ ọmọ Naijiria ninu to bẹẹ ti ọpọ fi n sọ pe ẹtanu lo mu ki irufẹ ọrọ bẹẹ jade lati ẹnu Tope Alabi si olorin to ṣẹṣẹ n bọ lẹyin rẹ.
Lẹyin ti fidio ọhun jade tan ni awọn eeyan bẹrẹ si n bu ẹnu atẹ lu Tope Alabi lori ayelujara, paapaa lojo opo Facebook ati Twitter, koda wọn ko jẹ ki oju opo Instagram rẹ sinnmi pẹlu.
Bo tilẹ jẹ pe ọpọ eeyan lo n reti ọrọ ti Alaseyori yoo sọ lori fidio Tope Alabi naa, ọrọ kankan ko jade lẹnu rẹ titi to fi sọ pe bii iya ni Tope Alabi jẹ si oun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Darandaran kan rí ẹ̀wọ̀n gbéré he ní Ekiti
- Nǹkan yan! Pásítọ̀ dáwọn ọmọ ijọ̀ dùbúlẹ̀ lórí pẹ̀pẹ́, ó ń nà wọ́n pẹ̀lú bẹ́lítì
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ sí ọkùnrin tó lù ará rẹ ní gbanjo ₦20m ní Kano
- Bí ìgbẹ́jọ́ Naira Marley ṣe lọ lọ́jọ́ Iṣẹ́gun rèé
- Boko Haram fi tipa fẹ́ mi fún ọkọ àmọ́ ìfẹ́ rẹ̀ gbóná lọ́kàn mi ni ń kò fi sá kúrò
- Kí ló dé tí Fayemi kò fí tẹ̀lé àwọn Gómìnà Yorùbá lọ kí Tinubu nílé?
- Wo àwọn gbajúmọ̀ míràn yàtọ̀ sí Tiwa Savage tí ọ̀rọ̀ fídíò ìbálòpọ̀ wọn ti bọ́ sí orí ayélujára ...
- Ó ṣe é ṣe ká má kópa nínú ìdìbò 2023 tí àtúntò Naijiria kò bá wáyé - Afenifere
- Àwọn amòfin ní ẹ̀yà Igbo dara pọ̀ mọ́ ẹjọ́ tí àwọn àgbààgbà Àríwá pè lórí Kanu àti IPOB
O ni "Iya wa ni Tope Alabi, bii iya lo si jẹ si gbogbo wa, a si ti di alabukun fun lati inu iṣẹ iranṣẹ rẹ...."
Ẹwẹ, lasiko ti rogbodiyan naa n lọ lọwọ ni ẹni gan to kọkọ gbe orin Oniduro naa jade, Tolulope Adelegan sọrọ soke lori orin ọhun ati igbesẹ to gbe lẹyin ti orin naa sọ Alaseyori di gbajumọ.
Adelegan ṣalaye fun BBC Yoruba pe lootọ, oun lo kọkọ gbe orin naa jade, ṣugbọn ẹmi mimọ lo ni ki oun dakẹ lẹyin ti orin naa sọ Alaseyori di gbajumọ, ti ọpọ si lero pe Alaseyori lo ni orin ọhun.




















