Timothy Adegoke: Kọmíṣọ́nà ọlọ́pàá Osun ní ọmọbíbí Rahmon Adedoyin tó ni ilé ìtura tí Adegoke kú sí, ló jù òkú rẹ̀ sígbó

Timothy Adegoke ati Rahmon Adedoyin

Oríṣun àwòrán, Timothy Adegoke/Rahmon Adedoyin/Facebook

Kọmiṣọnna ọlọpaa nipinlẹ Osun, Wale Olokode ti ni ọkan lara awọn afurasi ninu iku Timothy Adegoke, to jẹ akẹkọọ fasiti Obafemi Awolowo, ti jẹwọ bi iṣẹlẹ naa ṣe waye.

Afurasi naa, Roheem Adedoyin lo jẹ ọmọ ẹni to ni ile itura Hiltons Hotels and Resort, Ile-Ife, ni ọlọpaa ni oun lo ṣakoso bi wọn ṣe gbe oku naa kuro ninu ile itura lọ ju si inu igbo.

Ọga ọlọpaa nipinlẹ Osun ni Roheem ni alakoso ile itura naa ti Adegoke ti ku, to si wa nibẹ nigba ti iṣẹlẹ naa ṣẹlẹ, to si ṣeto bi wọn ṣe gbe oku rẹ kuro ni ile itura naa, ti wọn si lọ sin lai fi to ọlọpaa leti.

Lasiko to n sọrọ lori redio Rave FM, Osogbo ni Olokode ti ni, Roheem ti na papa bora, to si jẹ pe iwadii ọlọpaa lo jẹ ki wọn mọ ibi ti wọn gbe oku naa pamọ si.

''Ọkan lara awọn afurasi jẹwọ pe ọmọ Ramon Adedoyin ti orukọ rẹ n jẹ Roheem Adedoyin to jẹ ọmọ ẹni to ni ile itura naa, ti sa kuro ni ilẹ yii lati igba ti iṣẹlẹ naa ti ṣẹlẹ.

Àkọlé fídíò, Timothy Adegoke: Màmá olóògbé ní ògó ilé àwọn ni wọ́n pa, ikú rẹ̀ kò gbọdọ̀ já sásán

''Afurasi naa jẹwọ pe Roheem lo ṣakoso bi wọn ṣe lọ sọ oku arakunrin naa si inu igbo, ti oun naa si tẹle wọn pẹlu oṣiṣẹ agba meji to tẹle wọn lọ si inu igbo.''

''Ko si ẹnikẹni ninu awọn oṣiṣẹ yii to fi ẹjọ sun ọlọpaa, awọn mọlẹbi ti wọn bẹrẹ si ni wa ọkunrin naa, ti awọn ọlọpaa kogberegbe ti wọn si bẹrẹ si ni ṣe iwadii bi arakunrin naa ṣe di awati ninu ile itura, ti wọn si lo ri oku rẹ ninu igbo.''

N ko mọ bi Adedoyin se ka fọnran ohun ara rẹ silẹ lati ahamọ to wa, eyi gba ori ayelujara kan:

Olokode ni oun ko mọ nkankan nipa igbohunsafẹfẹ ti Adedoyin ṣe ni panpẹ ọlọpaa nibi to ti sọ wi pe oun ko jẹbi ẹsun ipaniyan ti wọn fi kan oun.

Amọ nibayii, awọn mọlẹbi ti kesi ileeṣẹ ọlọpaa lati salaye bi Adedoyin ṣe n jaye ọba ni ahamọ ọlọpaa nitori o jẹ ilumọọka ni awujọ.

Agbẹjọro mọlẹbi naa, Adekilekun ni awọn ti kesi ọlọpaa lati ri pe idajọ ododo jọba ni iwadii yii lai ṣe ojusaaju fun ẹnikẹni lori iṣẹlẹ yii.

O ni awọn ti bẹrẹ iwadii lori bi Adedoyin ṣe bẹrẹ si ni ṣe igbohunsafẹfẹ ninu ahamọ lasiko to wa ni ikawọ wọn.

''Ohun itiju lo jasi pẹlu bi ọpọlọpọ ọrọ ṣe n jade lati ẹnu awọn eniyan ti wọn fẹ gbeja ẹni to ni ile itura ti iṣẹlẹ naa ti ṣẹlẹ, Rahmon Adedoyin wi pe ko ṣẹ ẹsẹ kankan.''

''Ohun ti a fẹ ni ki onikaluku duro de idajọ ileẹjọ lori iṣẹlẹ yii lati sọ ẹni to jẹbi ẹsun yii tabi bẹẹkọ lai lo ọna ẹburu lati ma a ke gbajare si awọn eniyan lawujọ lati gbe ija wọn ja.''

Amin iyasọtọ kan

Bí àyẹ̀wò òkú Timothy Adegoke, akẹ́kọ̀ọ́ fásitì OAU tó kú sílé ìtura, ṣe wáyé rèé

Timothy Adegoke ati Rahmon Adedoyin

Oríṣun àwòrán, Timothy Adegoke/Rahmon Adedoyin/Facebook

Iroyin ni awọn onimọ nipa ayẹwo oku naa de ọgba ile iwosan ẹkọni Osun State University Teaching Hospital (UNIOSUNTH), Osogbo, ni nkan bi aago meji ọsan ni Ọjọ Aje

Awọn onimọ nipa ayẹwo oku ti ṣayẹwo iru iku to pa akẹkọkunrin ni fasiti Ọbafemi Awolowo University, ti Ile Ife.

Iroyin ni awọn onimọ nipa ayẹwo oku naa de ọgba ile iwosan ẹkọsẹ isegun fasiti ipinlẹ Osun (UNIOSUNTH) to wa nilu Osogbo, ni nkan bi aago meji ọsan Ọjọ Aje.

Amọ awọn onisegun naa ko gba awọn mọlẹbi, ati awọn oniroyin laaye si agbegbe naa, amọ wọn n woye bi o ṣe nlọ lati ileẹjọ.

Ninu ọrọ rẹ, agbẹnusọ fun ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Osun, Yemisi Opalola sọ fun awọn oniroyin pe wọn ko tete ṣe ayẹwo oku naa nitori awọn mọlẹbi sọ wi pe awọn fẹ ki aṣoju awọn wa nibẹ lasiko ayẹwo naa.

Àkọlé fídíò, Timothy Adegoke: Màmá olóògbé ní ògó ilé àwọn ni wọ́n pa, ikú rẹ̀ kò gbọdọ̀ já sásán

Bakan naa ni iroyin ni pe awọn mọlẹbi fa onimọ nipa ayẹwo oku ti yoo soju wọn silẹ, nigba ti awọn alayẹwo oku naa wa nibẹ ni ibi ayẹwo naa, ti gbogbo wọn si ri bi wọn ṣe ṣe ayẹwo naa.

Dokita Waheed Oluogun lati fasiti imọ ẹkọ iṣegun naa lo ṣe ayẹwo oku Timothy.

Amọ dokita naa ni awọn ọlọpaa ni oun yoo fi abajade ayẹwo naa ṣọwọ si ni nikan bi ọsẹ meji si mẹta si isinyii, ti esi ayẹwo naa ba jade.

Ninu ọrọ ẹbi Adegoke, eyi ti agbẹjọro Naheem Adekilekun kede sita, wọn ni o di igba ti ayẹwo oku naa ba jade ki awọn to sọ ọrọ kankan lori rẹ.

Adekilekun wa parọwa si awọn ileeṣẹ ọlọpaa pe ki wọn maṣe ṣe ojusaaju lori iṣẹlẹ naa, ki wọn si fi iya to tọ jẹ ẹni to ṣe iṣẹ laabi yii.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Timothy Adegoke ni wọn lo tẹ ọkọ leti wa si ipinlẹ Osun lati wa ṣe idanwo ni fasiti Obafemi Awolowo OAU , ki o to di awati ni Ọjọ Keje, Oṣu Kọkanla, ọdun 2021.

Lẹyin naa ni awọn ọlọpaa ri oku rẹ ninu igbo ni agbegbe to wa loju ọna Ede si Ife, lasiko ti wọn bẹrẹ si ni wa.

Ileeṣẹ ọlọpaa ni awọn afurasi mẹfa to jẹ oṣiṣẹ ile itura Hilton Hotels and Resort ati Ramon Adedoyin to ni ile itura naa. ni wọn ti mu lẹyin ti iwadii fihan pe lootọ ni Adegoke wa si ile itura naa lati gba yara, ki o to di awati.

Àkọlé fídíò, EndSARS Victims: Ìyá méjì nínú mẹ́ta ti kú nínú àwọn ọmọ tí ọlọ́pàá gbé àmọ́ torí ìwọ́de