Timothy Adegoke: Màmá olóògbé ní ògó ilé àwọn ni wọ́n pa, ikú rẹ̀ kò gbọdọ̀ já sásán

Àkọlé fídíò, Timothy Adegoke: Màmá olóògbé ní ògó ilé àwọn ni wọ́n pa, ikú rẹ̀ kò gbọdọ̀ já sásán

Akẹkọọ to n wa imọ kun imọ ni fasiti OAU ni Ile Ife ni Timothy Adegoke, idanwo si lo lọ se to fi duro sile itura Hilton to wa nilu naa.

Amọ lẹyin ọjọ diẹ lo di awati, ki wọn to wa ri oku rẹ lẹba ile itura naa, ti awọn ọlọpaa si ti ko awọn afurasi to jẹ osisẹ ile itura naa si ahamọ.

Koda, ẹni to ni ile itura naa, Ramon Adedoyin gan wa ni ahamọ ọlọpaa, ti iwadi si ti n lọ lọwọ.

Nigba ti BBC Yoruba de ilu Eruwa, tii se ilu abinibi oloogbe Adegoke, se ni awọn obi rẹ, ọmọ aya atawọn aburo rẹ n wa ẹkun mu.

Ninu ọrọ rẹ, aya oloogbe salaye bi ọkọ rẹ se rin, to fi se agbako iku ojiji, to si ni oun gbọ pe wọn ri aje lara ọkọ oun ni wọn se lo o.

Bakan naa ni awọn obi Timothy ni ogo idile awọn ni ọkunrin naa jẹ, iku rẹ ko si gbọdọ ja sasan, gbogbo ẹni to ba si lọwọ ninu dida ẹmi rẹ legbodo, ni ko gba idajọ to yẹ.

Nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ lori isẹlẹ naa, agbẹnusọ fun ileesẹ ọlọpaa ipinlẹ Osun, Yemisi Opalola tako ọpọ ahesọ ọrọ to n lọ lori iku oloogbe naa lori ayelujara.

Opalola ni irọ to jinna sootọ ni pe wọn pa Timothy Adegoke lati fi se etutu ni nitori o ni ẹyin ara oloogbe naa kankan ko di awati lara rẹ.