Lóòtọ́ la mú ọkùnrin kan pẹ̀lú agbárí èèyan, ṣùgbọ́n kìí ṣe pásítọ̀-Ọlọ́pàá Ondo

Awọn ọlọpaa ati ọdaran

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Ondo ti ṣalaye wi pe lootọ ni ọwọ awọn tẹ arakunrin kan pẹlu agbari eniyan ati apa meji ni ikawọ rẹ.

Iroyin kan n ja rayinranyin lori ayelujara pe pasitọ kan ti bọ si panpẹ awọn ọlọpaa nigba ti wọn muu pẹlu ika ọwọ mẹtadinlogun ati oniruuru ẹya ara eniyan miran l'agbegbe Alagbaka ni ilu Akurẹ.

Iroyin naa fi kun pe awọn ọlọpaa ikọ SARS kan tun kọlu agbabọọẹu kan nibẹ, ati pe pasitọ ni ọkunrin ti wọn ba ẹya ara eniyan lọwọ rẹ.

Ṣugbọn nigba to n ba BBC Yoruba sọrọ, alukoro ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Ondo, Ọgbẹni Fẹmi Joseph ṣalaye pe irọ funfun balau ni iroyin naa ati pe ko si igba kankan ti awọn ọlọpaa ni ipinlẹ naa mu pasitọ kankan pẹlu ẹya ara eniyan.

O ni ọwọ awọn ọlọpaa ipinlẹ naa tẹ arakunrin, ẹni aadọta ọdun kan ni owurọ oni ni ilu Idoani pẹlu agbari eeyan kan ati apa meji ti wọn ti dana sun guruguru.

Àkọlé fídíò, Omidan jáde láyé lẹ́yìn tí ìlú lù ú, jáa sí ìhòhò lórí ẹ̀ṣẹ̀ tí kò ṣẹ̀

Ọgbẹni Joseph tun sọ pe afunrasi naa ṣalaye pe ẹnikan ti orukọ rẹ n jẹ Alhassan lo ran oun, ti ileeṣẹ ọlọpaa si ti mu awọn mejeeji bayii.

O wa rọ awọn araalu lati jinna sawọn to n gbe iroyin ofege to lee da họwuhọwu silẹ lawujọ.