Kogi Crisis: Abaribe ní ìpìlẹ̀ Nàíjíríà ń mì pẹ̀lú ìwà ọ̀yájú sí ofìn ní Kogi

Adajọ agba n bura fun igbakeji gomina tuntun

Oríṣun àwòrán, @EkeleHaruna

Adajọ agba nipinlẹ Kogi, Adajọ Nadir Ajana ti bura fun Edward Onoja gẹgẹ bii igbakeji gomina tuntun fun ipinlẹ Kogi.

Igbesẹ yii waye lẹyin ti ile asofin ti se ayẹwo tan fun igbakeji gomina tuntun naa.

Lasiko ayẹyẹ ibura naa, olori ile asofin ni Kogi, Matthew Kolawole sapejuwe iyansipo Onoja gẹgẹ bii ere jijẹ olootọ ati olufọkansin si gomina lasiko to fi jẹ olori awọn osisẹ lọọfisi gomina.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O wa rọ igbakeji gomina tuntun naa lati maa tubọ tẹle oju ọna otitọ ati isẹ asekara eyi to mu de ipo giga ọhun.

Igbakeji gomina tuntun n tẹriba niwaju ile asofin lasiko ibura

Oríṣun àwòrán, @EkeleHaruna

Ọjọ Ẹti to kọja ni ile asofin ipinlẹ Kogi yọ Simon Achuba gẹgẹ bii igbakeji gomina nipinlẹ naa lẹyin ti igbimọ oluwadi to tanna wadi rẹ jabọ pe ko ni ẹsẹ kankan lọrun.

Wayi o, olori ọmọ ẹgbẹ oselu to kere julọ nile asofin agba ilẹ wa, Senatọ Eyinnaya Abaribe ti kesi aarẹ Muhammadu Buhari lati dasi ọna to lodi sofin ti wọn gba yọ igbakeji gomina nipinlẹ Kogi.

Igbakeji gomina tuntun ati gomina Yahaya Bello

Oríṣun àwòrán, @EkeleHaruna

Atẹjade kan ti Abaribe fisita nilu Abuja ni eyi ti jẹyọ pẹlu afikun pe, niwọn igba tijọba ipinlẹ Kogi ti kuna lati daabo bo ofin ilẹ wa, o yẹ ki aarẹ Buhari da si ọrọ naa lai fi ti ẹgbẹ oselu se.

Abaribe ni pẹlu iwa ọyaju tile asofin ipinlẹ Kogi hu si ofin ilẹ wa naa, a jẹ pe ipilẹ orilẹede Naijiria n mi ree.