Amotekun news: Báwo lọ̀rọ̀ ṣe jẹ́ tí wọ́n fi ní ikọ̀ tó ń dáàbò bo ìlú yìnbọn pa èèyàn méjì n'Ibadan?

Adari ikọ Amotekun ni ẹkún Guusu-Iwọ Oorun ilu Ibadan sọ fun BBC Yoruba pe ohun tawọn n lọ mọ awọn lẹsẹ ko ri bẹẹ bi ko ṣe pe wọn kan fẹ ba wọn lorukọ jẹ.
Adari ikọ Amotekun ipinlẹ Oyo, Olayinka Olayanju sọ pe lootọ ni awọn oṣiṣẹ Amotekun gbọ pe rogbodiyan kan bẹ silẹ lagbegbe Born Photo si Isale Osi, ti awọn ọmọ ẹgbẹ OPC n gbiyanju lati pari.
Àwọn eeyan kan lo fẹsun kan ikọ Amotekun ni ipinlẹ Oyo pe awọn oṣiṣẹ wọn yinbọn pa eeyan meji lagbegbe Asaka, ni ilu Ibadan.
Gẹgẹ bi ohun ti a gbọ, wọn ni iṣẹlẹ naa waye ni orita Ike-Olu l'Ọjọbọ to kọja, lẹyin ti ọgbẹni kan to jẹ ọmọ ẹgbẹ Oodua Progressive Congress, OPC to tun ṣẹṣẹ darapọ mọ ikọ Amotekun yinbọn lu eeyan meji nitori aawọ kan to waye laarin wọn.
Ṣugbọn atẹjade kan lati ọdọ Amotekun ti sọ pe oṣiṣẹ awọn kọ lo yin ibọn ọhun.
- Kí ló tún ṣe Òṣèré fíìmù Yorùbá míì tó ń gba ẹ̀jẹ̀ àtomi níléèwòsàn?
- Ọ̀rọ̀ ààbò kìí se èyí tí a lé fí gbèdéké sí - Femi Adesina
- Dùndú rẹ ń láta! Ó yẹ kí àwọn ọlọ́pàá mú Lere Olayinka fún ìwà ọ̀daràn - Oyo PDP
- Kí nìdí tí Ooni Adeyeye Ogunwusi fi gbé Àrẹ̀mọ ilẹ̀ Oodua wọ ṣọ́ọ̀ṣì?
- Èèyàn mẹ́ta jẹ́ Ọlọrun nípè, 501 míràn tún fara kásá Coronavirus ní Naijiria

Oríṣun àwòrán, @Slaypappii
O ni asiko ti wọn de ibẹ ni wọn ṣakiyesi pe awọn janduku kan atawọn ọmọ OPC naa ti n kọlu ara wọn, ti wọn si yinbọn lemọlemọ, ṣugbọn o ni Amotekun lo pana aawọn ọhun, ti wọn si fi ṣikun ofin mu awọn afurasi kan ti wọn fa le awọn agbofinro Operation Burst lọwọ.
Adari Amotekun naa sọ siwaju si pe lẹyin ti awọn pana rogbodiyan naa tan ni awọn janduku ọhun lọ kọlu ọmọ ẹgbẹ OPC kan to tun jẹ oṣiṣẹ ikọ Amotekun.
Olayanju sọ pe o ṣeni laanu pe awọn ileeṣẹ iroyin kan ti gbe iroyin jade lara oṣiṣẹ ikọ Amotekun yinbọ pa awọn eeyan kan, ṣugbọn iwadii ti bẹrẹ lati yanju ọrọ naa.
Ẹwẹ, ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ti sọ pe ikọ Amoteku ko lọwọ ninu iku ẹnikẹni lagbegba ibi ti iṣẹlẹ naa ti waye.
- Wo ìdí tí ọmọ ọdún mẹ́wàá ṣe ti àbúrò rẹ̀ ọmọ ọdun kan àbọ̀ sínú kàǹga
- Atiku figbe bẹnu, ó ní kí ìjọba ó dín ìrìnnà ọkọ̀ òfúrufú láàrín ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti Nàìjíríà kù nítorí COVID-19
- Buhari, pàṣẹ fún Pantami kó lọ tọwọ́ ọmọ rẹ̀ bọ aṣọ lórí ìforúkọsílẹ̀ NIN-SERAP
- Àwọn agbébọn tún gbìyànjú láti gbé akẹ́kọ̀ọ́ ilé Keu 80 ní Katsina
Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa Oyo, Olugbenga Fadeyi ni wọn fi iṣẹlẹ naa to agọ wọn to wa ni Mapo leti.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni awọn meji ti wọn padanu ẹmi wọn ni Asaka ku lẹyin ti awọn kọlọrọsi kan ṣakọlu si wọn nitori wọn kọ lati darapọ mọ ẹgbẹ OPC.
Lẹyin naa lo ni iku wọn ko ni nnkankan ṣe pẹlu ikọ Ametekun.
















