Oyo PDP: Ó yẹ kí àwọn ọlọ́pàá mú Lere Olayinka torí ó ń fi ara rẹ̀ sí ipò tí wọn kò yàn án sí

Oríṣun àwòrán, @thesignalng
Ẹgbẹ oṣelu PDP, ẹka ti ipinlẹ Oyo ti ke si awọn agbofinro lati fi ṣikun ofin mu ọgbẹni Lere Olayinka, to jẹ adari ikọ ipolongo ẹgbẹ naa ni iha Guusu-Iwọ Oorun Naijiria lori ẹsun pe o n fi ara rẹ si ipo ti wọn ko yan si.
Nigba to n ba ileeṣẹ iroyin abẹle Daily Independent sọrọ, agbẹnusọ ẹgbẹ naa nipinlẹ Oyo, Akeem Olatunji sọ pe, agbẹnusọ lasan ni Olayinka jẹ si gomina ipinlẹ Ekiti tẹlẹ, Ayodele Fayose.
O ni ko si ẹnikẹni to yan Olayinka si ipo kankan ninu ẹgbẹ PDP ni iha Guusu-Iwọ Oorun Naijiria, nitori naa ohun to n ṣe ko ba ofin ẹgbẹ naa mu.
- Báyìí ni Àrẹ̀mọ Ooni Adeyeye Ogunwusi ṣe wọ ṣọ́ọ̀ṣì fún ìgbà àkọ́kọ́ láti bá bàbá rẹ̀ ṣe ìdúpẹ́ ìwúyè
- Atiku figbe bẹnu, ó ní kí ìjọba ó dín ìrìnnà ọkọ̀ òfúrufú láàrín ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì àti Nàìjíríà kù nítorí COVID-19
- Wo ìdí tí ọmọ ọdún mẹ́wàá ṣe ti àbúrò rẹ̀ ọmọ ọdun kan àbọ̀ sínú kàǹga
- Buhari, pàṣẹ fún Pantami kó lọ tọwọ́ ọmọ rẹ̀ bọ aṣọ lórí ìforúkọsílẹ̀ NIN-SERAP
Olatunji ṣalaye pe gbogbo ọgbọn ti Olayinka ati ọga rẹ n da ni lati da wahala silẹ ninu ẹgbẹ PDP ki wọn to sa lọ darapọ mọ ẹgbẹ APC.
Gẹgẹ bo ṣe sọ, o ni "Lere Olayinka ni agbẹnuso gomina ipinlẹ Ekiti tẹlẹ, iyẹn Ayo Fayose, kii ṣe aṣoju tabi oṣiṣẹ ẹgbẹ PDP."
"Ta lẹni to fi si ipo adari ikọ ipolongo ẹgbẹ naa ni iha Guusu-Iwọ Oorun Naijiria? O kan mọọmọ fi ararrẹ si ipo naa ni."
Olatunji tẹsiwaju pe ohun ti Lere Olayinka ṣe jẹ iwa ọdaran, nitori ko ba ofin mu ko maa pe ara ni ẹni ti kò jẹ tabi ko fi ara rẹ si ipo ti wọn ko yan si.
O pari ọrọ rẹ pe "a ti kilọ fun Lere Olayinka ati ọga rẹ lati jawọ ninu fifi idarudapọ sinu ẹgbẹ osẹlu PDP nitori a mọ pe wọn le darapọ mọ ẹgbẹ keji ti a ba le wọn kuro ninu ẹgbẹ wa."
- Àwọn agbébọn tún gbìyànjú láti gbé akẹ́kọ̀ọ́ ilé Keu 80 ní Katsina
- Báwo ni mo ṣe fẹ́ fi ìyàwó àfẹ́sọ́nà mi akáta hàn fáwọn òbí mi?
- Ọmọ Risikat olójú búlúù méjèéjì jẹ̀bùn oríire àti ìfà ńlá
- Njẹ́ ó wù ọ́ láti jànfàání ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ àjọ Commowealth 2020/2021? Wo ọ̀nà àbáyọ níbí
- Òṣèré tíátà Yorùbá yìí la orí mọ́lẹ̀ nígbà tó ń ṣe sinimá lọ́wọ́














