Akure Death: Ọmọ ọdún mẹ́wàá ṣàlàyé ìdí tó ṣe ti àbúrò rẹ̀ tó jẹ́ ọmọ ọdun kan àbọ̀ sínú kàǹga

Adamu

Oríṣun àwòrán, @NtaAdo

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ondo ti fi ṣinkun ofin mu ọmọdebinrin ẹni ọdun mẹwaa kan ti wọn fẹsun ipaniyan kan lagbegbe Owode, ni ijọba ibilẹ Ariwa Akure.

Wọn fẹsun kan afurasi naa, ti awọn obi rẹ jẹ ọmọ bibi ipinlẹ Sokoto, pe o ti aburẹ rẹ ọkunrin sinu kanga.

Bo tilẹ jẹ baba kan naa lo bi awọn mejeji, iya ọtọtọ lo bi wọn.

Àkọlé fídíò, 'Pásítọ̀ ló sọ fún mi pé Ọlọ́run pè mí láti di Olokun tó ń bọ omi'

Iroyin ni lẹyin to ti ọmọ ọdun kan ati oṣu mẹjọ naa sinu kanga tan lo sọ fun baba rẹ pe wọn ti ji ọmọ ọhun gbe.

Kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Ondo, Bolaji Salami ni iṣẹlẹ naa waye lọjọ karundinlogun, oṣu Kejila, ọdun 2020.

Well in Kano

Oríṣun àwòrán, @Naija_PR

Salami ṣalaye fun awọn oniroyin pe "o kọkọ sọ fun baba rẹ pe awọn gbọmọ-gbọmọ lo ji aburo rẹ ọhun gbe ko to jẹwọ pe ọmọ naa wa ninu kanga."

Nigba to n sọrọ lori idi to fi ti aburo rẹ sinu kọnga, ọmọ ile iwe alakọbẹrẹ naa sọ pe ounn ko mọ pe ohun ti oun ṣe yoo yọri si iku ọmọdekunrin naa.

Lẹyin naa lo sọ pe oun ti i sinu kanga lati gbẹsan bi iya rẹ ṣe maa n fi iya jẹ oun.

O ni iyawo baba oun naa maa n fi iya jẹ oun leyin ti ija bẹ silẹ laarin baba ati iya oun, ti baba oun si gbe obinrin naa niyawo.

Àkọlé fídíò, Risikat Moromoke Azeez: Inú èmí àti Òbí mi dùn nígbà ti Risi bí ọmọ olójú búlù- Wasiu

Bakan naa lo tun sọ pe baba oun fẹran oloogbe naa ju oun lọ, nitori naa ni oun ṣe ti ọmọ naa sinu kanga ṣugbọn oun ko mọ pe yoo mu ẹmi rẹ lọ.

Ẹwẹ, kọmiṣọna ọlọpaa ipinlẹ Ondo ti sọ pe afurasi ọhun yoo foju bale ẹjọ laipẹ.

Àkọlé fídíò, Zlatan: Ọ̀rẹ́ ni mo sìn lọ ‘studio’ tí mo fi bẹ̀rẹ̀ orin lẹ́yìn tí mo kùnà ìdánwò WAEC