Lagos Theft: Ẹrù olè gbé ẹ̀ṣọ́ ilé wọ kóló olọ́pàá

Oríṣun àwòrán, RRS
Ikọ kogberegbe ti ileeṣẹ Ipinlẹ Eko (RRS) ti mu awakọ kan ti wọn fẹsun kan wi pe o ra ẹru ole - awọn nkan ikọle ti awọn oṣiṣẹ kan maa n ji ni agbegbe Lekki.
Atẹjade RRS kan ni ọwọ tẹ afẹsunkan naa Hassan Abubakar ẹni ọdun mejilelọgbọn nigba to n wa ọkọ akẹru kan to fi ko apo simẹnti mọkanlelogun ni bi aago marun aabọ aarọ nigba ti awọn n kaakiri adugbo naa.
Àwọn ìròyìn mìíràn tí ẹ lè nífẹ̀ẹ́ sí:
Ṣugbọn nigba ti wọn pe ẹni to sọ pe o ran oun niṣẹ, Abubakar bẹrẹ si ni ka bi ẹyẹ. O ni ọkan lara wọn ọdẹ to n ṣọ ibi ti wọn ti n kọ ile naa, Adamu Ibrahim lo ji simẹnti naa.
Nigba ti ọwọ ba Adamu, o ni ẹni to ni ile ti wọn n kọ na jẹ oun ni ẹgbẹrun marundinlọgbọ owo oṣu. O ni owo naa ni oun fẹ gba pada ti oun fi ko awọn simẹnti naa.
RRS ni wọn ti fa awọn afẹsun kan naa le ẹka to n ṣe iwadii awọn ẹsun ni Ipinlẹ eko (SCID) lọwọ fun iwadii.









