Alaafin: Ó wu àwọn ìyàwó mi ni wọ́n fẹ́ mi, èmi kọ́ ni mo dẹnu ìfẹ́ kọ wọ́n

Oríṣun àwòrán, alaafin_oyo/Instagram
Alaafin ilu Ọyọ, Ọba Lamidi Adeyẹmi, sọ pe oun ko kọnu ifẹ kọ obinrin kankan ri.
Ọba Adeyẹmi, ninu ifọrọwanilẹwo kan to ṣe pẹlu iwe iroyin Punch sọ pe, o wu awọn iyawo oun lati fi oun ṣọkọ nitori pe oun ran wọn lọ sileewe.
O sọ pe ''mo sọ fun wọn pe ki wọn ma a lọ, ṣugbọn wọn sọ pe awọn ṣa a fẹ duro ti mi l'aafin gẹgẹ bi iyawo mi.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mo fẹ́ ọkọ mi torí bó se ń kọrin, kìí se torí owó - Ìyàwó Aràrá
- Mo fẹ́ kí àyẹyẹ ìgbeyàwó mi dùn ni mo se bú sẹ́kún - Ọkọ ìyàwó ẹlẹ́kún
- Samuel Ladoke Akintọla jẹ́ Agbẹjọ́rò àti Akọ̀ròyìn tí ọ̀rọ̀ dá lẹ́nu rẹ̀
- Hubert Ogunde rèé, baba àwọn òsèré tíátà
- Ìyàtọ̀ wà nínú ìlépa àwọn òṣèré tíátà ayé àtijọ́ àti ìsisìnyí-Papalolo
- Iléesẹ́ ológun ń retí bàálù 18 látọ́dọ̀ Amẹrika fi kojú Boko Haram
- Aláàfin ń se ọgọ́rin ọdún, àwọn àwòrán mánigbàgbé
"Eyi to gboye imọ ijinlẹ to kere ju lọ ni iwe ẹri agba nileewe gbogboniṣe, Higher National Diploma (HND).''
Ọba alaye naa ṣalaye pe koda, ọrẹ ni iyawo oun akọkọ jẹ pẹlu aburo oun obinrin. Aburo rẹ naa lo si fi awọn mejeeji mọ ara wọn.
Alaafin ni ọpọlọpọ awọn ọdọbinrin ni Olori, ti awọn eniyan si maa n wo o pe kini awọn obinrin naa n ri ti wọn fi n fẹ ẹ.
Amọ Ọba Adeyẹmi ni Ọlọrun ran oun lọwọ lati tọ awọn iyawo oun, ati lati maa dari wọn lai jẹ wi pe igbeyawo naa tuka, tabi ki ija orogún o da ile oun ru.

Oríṣun àwòrán, Alaafin Oba Lamidi Adeyemi III
''Mi o mọ bi wọn ṣe n lepa tabi dẹnu ifẹ kọ obinrin. Ohun kan ni pe, mo mọ bi mo ṣe n jẹ ki obinrin o pẹ lọwọ mi, paapa obinrin to rẹwa.''














