AWCON: Nàìjírìa gba ife ẹ̀yẹ AWCON fún ìgbà kẹsàn-án

Super Falcons

Oríṣun àwòrán, @NGsuper_falcons

Àkọlé àwòrán, Ìdùnnú ṣubú layọ̀ fún àwọn ọmọ orílẹ̀èdè Nàìjíríà
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 2

Aarẹ Muhammadu Buhari ti ki awọn agbabọọlu ikọ Super Falcons ku oriire bi wọn ṣe jawe olu bori ninu aṣekagba idije ife ẹyẹ ilẹ Afirika ti àwọn obinrin lọjọ Abamẹta

Buhari fi idunnu rẹ han lori bi ikọ agbabọọlu naa ṣe gba ife ẹyẹ idije naa nigba kẹsan-an .

Skip X post, 1
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 1

Nàìjírìa fakọyọ nínú ìdíje AWCON

Nàìjírìa ti gba ife ẹ̀yẹ ere bọọlu awọn ilẹ Afirika AWCON lẹ́ẹ̀kẹsàn an lẹyin ti wọn na South Africa pẹlu ami ayo mẹrin si mẹta nínú ifẹsẹwọnsẹ aṣekágba ìdíje náà.

Ọọmi odo sodo ni wọn ta nigba ti iṣẹju aadọrun akọkọ kọkọ pari, lẹyin naa ni wọn tun gba bọọlu fun ọgbọn iṣẹju miran.

Skip X post, 2
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 2

Ṣugbọn ko sẹni to tun rayo gba wọle ara wọn lẹyin ọgbọn iṣẹju naa, lọrọ ba di wo mi ki n gba siọ ti wọn n pe ni pẹnariti.

Nibi pẹnariti ri gan ni Naijiria ti fagba han South Africa pẹlu ami ayo mẹrin si mẹta 4-2.

Skip X post, 3
Allow X content?

This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of X post, 3

Ikọ agbabọọlu Naijiria ti gba ife ẹyẹ naa lẹẹmẹsan an ọtọtọtọ bayii, nigba ti alatako wọn South Africa ko tii gba ri rara.

Amaju Pinnick ati Asisat Oshoola

Oríṣun àwòrán, @NGsuper_falcons

Àkọlé àwòrán, Ìgbà kẹsàn-án rèé tí wọn yóò gba ife ẹ̀yẹ náà

Ikọ Super Falcons ko tii fidi rẹmi ri ninu ifẹsẹwọnsẹ aṣekagba idije ife ẹyẹ ọhun, ṣugbọn South Africa ti kuna lẹẹmẹrin ti wọn ti kopa ninu aṣekagba idije naa

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Igba keji ree ti Naijiria ati South Africa yoo waako ninu ifẹsẹwọnsẹ aṣekagba idije ife ẹyẹ ere bọọlu awọn obinrin nilẹ adulawọ.

Naijiria ati South Africa

Oríṣun àwòrán, Instagram/Super Falconspage

Àkọlé àwòrán, Idije Awcon

Ikọ Super Falcons lo jawe olubori pẹlu ami ayo meji sodo nigba ti wọn pade ninu idije ti ọdun 2000 nilu Johannesburg lorilẹede South Africa.

Ẹ rant i wi pe South Africa lu Naijiria pẹlu ami ayo kan sodo ninu ifẹsẹwọnsẹ akọkọ awọn mejeeji ninu idije ti ọdun yii lorilẹede Ghana.