Nigeria Election 2023: Tani Rabiu Kwankwaso tó ń díje dupò ààreͅ ní eͅgbéͅ òsͅèlú NNPP?

Rabiu Kwankwaso

Rabiu Musa Kwankwaso to jeͅ eͅni oͅdun meͅrindinlaadoͅrin lo n dije du ipo lati di ipo aareͅ mu lorileͅede Naijiria ni idibo gbogboogbo ti yoo waye ni Oͅjoͅ Karundinloͅgbon, Osu Keji, oͅdun 2023.

Kwankwaso jeͅ eniyan to feͅran lati maa woͅ fila pupa ni gbogboogbo igba, lati fi asͅeyoͅri reͅ han.

o fi igba kan jeͅ minisita teͅleͅri fun eͅka Ologun, o ti jeͅ seͅnatoͅ ri fun igba meji ati gͅgͅbi gomina ipinleͅ Kano ni eemeji.

Rabi'u Musa Kwankwaso darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu Social Democratic Party (SDP), ni ọdun 1992, ti wọn si dibo yan an gẹgẹ bi aṣoju ni Ile Igbimọ Aṣofin to n ṣoju ẹkun Madobi.

Lẹyin naa lo darapọ mọ ẹgbẹ oṣelu Democratic Party of Nigeria (DPN) lasiko iṣejọba Ọgagun Sani Abacha.

Ọdun 1998 ni Kwankwaso darapọ mọ PDP, to si jẹ gomina ipinlẹ Kano ni May 29, 1999 si May 29, 2003, to tun wọle pada ni ẹlẹẹkeji ni ọdun 2011.

Ni ọdun 2013 lo yapa kuro ni PDP lọsi APC, amọ to kuna ninu idibo abẹle fun ipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu naa.

Ni ọdun 2018 ni Kwankwaso pada si PDP amọ to tun fidirẹmi ni idibo abẹle sipo oludije aarẹ ni ẹgbẹ naa, eleyii ti Atiku Abubakar bori.

February 22, 2022 ni o lọ da ẹgbẹ tuntun kalẹ, New Nigeria Peoples Party, to si bori gẹgẹ bi oludije sipo aarẹ labẹ ẹgbẹ oṣelu naa.

Amoͅ onimoͅ nipa eto oselu , Chisom Ugbari ni Kwankwaso nilo lati ni awoͅn alatileͅyin ni guusu Naijiria lati le di ipo aareͅ mu.

Bakan naa ni woͅn gba Kwankwaso ni imoͅran lati darapoͅ moͅ Peter Obi ti Labour Party ki woͅn le da ero woͅn pada.

Amoͅ Kwankwaso lasiko to n ba BBC soͅroͅ ni Peter Obi kere si oun ninu oͅroͅ osͅelu, nitori oun ti pe ninu oͅroͅ oselu.

Asͅeyoͅri ni eto eͅkoͅ…

Rabiu Kwankwaso

Ninu oͅroͅ reͅ alatileͅyin Kwankwaso, Ibrahim Sharada ni okiki Kwankwaso kii se ni ila oorun Naijiria nikan.

Bakan naa lo ni Kwankwaso peͅlu awoͅn oludije meͅrin to pegede juloͅ ni Naijiria, to si seese ko gbe igba oroke bii oͅdun 1999 to di ipo gomina mu ni ipinleͅ Kano.

Asiko yii ni opin de ba ijoͅba Ologun ni Naijiria, amoͅ ti ko I tii beͅreͅ si ni de fila pupa reͅ nigba naa loͅhun.

Igba isejoͅba aareͅ Obasanjoͅ lo fi si ipo Minisita fun ileesͅeͅ Ologun, leͅyin to kuna idibo sipo gomina ni oͅdun 2003.

Ipo yii lo di mu titi di oͅdun 2007, ti alaafia job ani Naijiria.

Àwọn ta ló ń díje láti tukọ̀ Naìjíríà?

Mọ̀ síi nípa àwọn tó ń du ipò ààrẹ Nàìjíríà

Ya olùdíje kan nítorí kí o lè kà nípa wọn

Bola Tinubu

All Progressives Congress (APC)

  • Ọjọ́ orí: 70
  • Ó gba oyè nípa ìmọ̀ ìṣirò ní fásitì ìpínlẹ̀ Chicago (Chicago State University)
  • Ó ṣe gómìnà ìpínlẹ̀ Eko fún sáà méjì láti 1999 sí 2007
  • Ó ṣojú [wọ̀ Oòrùn ìpínlẹ̀ Eko ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà láti 1992 sí 1993.
  • Ó jẹ́ èèyàn kan tó ti pẹ́ nhí ìdí òṣèlú Nàìjíríà, ìgbà àkọ́kọ́ tí yóò du ipò ààré nìyí.
  • ìgbógun ti ìṣèjọba sójà
  • Mú ìdàgbàsókè bá owó tó wọlé fún ìpínlẹ̀ Eko ní ọ̀nà tó ju ìlọ́po mẹ́rin lọ láti N22.2 blilion ní 1999 sí N220.9 bíllion ní 2007.
  • Ó ṣiṣẹ́ bíi ọ̀gá tó ń ṣe àyẹ̀wò ìwé owó, lẹ́yìn náà ló ṣe iṣẹ́ akápò ní iléeṣẹ́ Mobile Producing Nigeria, ọ̀kan lára iléeṣẹ́ epo tó tóbi jù ní Nàìjíríà.
  • Láti ṣé àlékún ọjà tí Nàìjíríà ń tà síta àti láti dín ìgbẹ́kẹ̀lé Nàìjíríà kù lóríiohun òkèrè.
  • Láti sọ àìníṣẹ́ ṣe láàrin àwọn ọ̀dọ́ di ìlàjì láàrin ọdún mẹ́rin àti láti pèsè iṣẹ́ mílíọ́nù kan nípa ìmọ̀ ẹ̀rọ kọ̀pútà láàrin ọdún méjì.
  • Mú àyípadà bá ètò ìdájọ́ kó lè mójútó ìdènà ìrúfin àti ṣe àlékún ìfọkàntán lórío àwọn agbófinró.

Atiku Abubakar

Peoples Democratic Party (PDP)

  • Ọjọ́ orí: 76
  • Igbákejì ààrẹ Naìjíríà láti ọdún 1999 sí 2007.
  • Ó kàwé gboyè eléèkejì (masters) lórí àjọṣepò àwọn orílẹ̀èdè (International Relations) láti fásitì Anglia Ruskin University , UK.
  • Ó jẹ́ ẹni tó ṣe iṣẹ́ aṣọ́bodé rí kó tó di olóṣèlú láti nǹkan bíi ọdún 1980.
  • Ó du ipò ààrẹ náà ní ẹmaàrú ùn ní ọdún 1993, 2007,2011, 2015 àti 2019, ṣùgbọ́n kò wọlé.
  • Òun ló dá fásitì Amẹ́ríkà ti Nàìjíríà (American University of Nigeria) silẹ̀, fasitì náà fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́bìnrin Chibok ní ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́.
  • Oníṣòwò tó ṣe àṣeyọrí tó ní okòwò níbi ọ̀rọ̀ epo, ọ̀gbìn, bánkì àti ògùn.
  • Ètò títa iléeṣẹ́ ìjọba tó ní àríyànjiyàn nínú.
  • Fún àwọn aládáni ní ipa tó pọ̀ nínú ètòi ọrọ̀ ajé.
  • Fún ìṣọ̀kan orílẹ̀èdè ní agbára síi nípa ìṣe déédéé àti ìdájọ́ òdodo láàrin àwọn ẹ̀yà tó ń gbé ní Nàìjíríà.
  • Ṣe àtúntò ètò ìṣèjọba Nàìjíríà.

Peter Obi

Labour Party

  • Ọjọ́ orí: 60
  • Gómìnà tó ṣe sáà méjì ní ìpínlẹ̀ Anambara láti ọdún 2007 sí ọdún 2014.
  • Ó du ipò igbákejì ààrẹ ní ọdún 2019.
  • Oníṣòwò tó kàwé gboyè nípa ìmọ̀ ẹ̀kọ́ ọgbọ́n (Philosophy) ni University of Nigeria Nsukka.
  • "o bá ìpínẹ̀ rẹ̀ dá okòwo ''sub soveriegn wealth fund '' tó tó $156 million ní ìgbà tó fẹ́ fi orí oyè sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bíi gómìnà.
  • Ó gbé ìpínlẹ̀ Anambara lọ sí ipò kínní láti ipò kẹrìndínlọ́gbọ̀n nínú àwọn ìpínlẹ̀ Nàìjíríà lórí ìdánwò NECO àti WAEC.
  • Ó ní àwọn ṣọ́ọ̀bù alágbàtà kan tó fún ẹgbẹgbẹ̀rún èèyàn ní iṣẹ́.
  • Ó ṣèlérí láti kó àkóyawọ́ la'ti ríi pé ìjọba gbógun ti ìwà àjẹbánu.
  • Ó ṣèlérí láti gbé Nàìjíríà dé ibi ṣíṣe nǹkan láti ibi lílo nǹkan.
  • Ó ṣèlérí láti gbé ọlá fún ìdàgbàsókè àwọn èèyàn nípasẹ̀ fífi owó sí ẹ̀kọ́ ìmọ̀ ẹ̀rọ àti sáyẹ́sì, ètò ìlera àti àwọn nǹkan amáyédẹrùn.

Rabiu Kwankwaso

New Nigeria Peoploes Party (NNPP)

  • Ọjọ́ orí:66
  • Mínísítà fún ètò ààbò láti ọdún 2003 sí ọdún 2007
  • Gómìnà ìpínlẹ̀ Kano láti ọdún 1999 sí ọdún 2003, àti láti ọdún 2011 sí ọdún 2015.
  • Ó ṣojú agbègbè Madobi ní ilé ìgbìmọ̀ aṣojúṣòfin n;i ọdún 1992 àti ààrin Kano ní ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin àgbà láàrin ọdún 2015 sí ọdún 2019.
  • Ó kàwé gboyè PhD ní orí ìmọ̀ ẹ̀rọ ilé kíkọ́ láti fásitì Sharda ní India.
  • Ètò ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ àti ìtọrẹ.
  • Ó ṣe àfikúnb iye àwọn tó wọ ilé ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀ láti mílíọ́nù kan lọ́dún 2011 sí mílíọ́nù mẹ́ta ní ọdún 2015 nígbà tó kúrò lórí oyè.
  • Ó pèsè oúnjẹ ọ̀fẹ́ àti aṣọ ilé ẹ̀kọ́ ọ̀fẹ́ fún àwọn akẹ́kọ̀ọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ alákọ́bẹ̀rẹ̀.
  • Ó dá fásitì Sáyẹ́nsì àti ìmọ̀ ẹ̀rọ ìpínlẹ̀ Kano sílẹ̀ ní Wudil sílẹ̀. Ó tún dá Northwestern University sílẹ̀. Àwọn fásitì ìpínlẹ̀ Kano méjéjì.
  • Ó ṣe ìlérí láti pèsè iṣẹ́ nípasẹ̀ ìdókòwò lórí ètò ọ̀gbìn.
  • Kojú ètò ààbò tó mẹ́hẹ.
  • Ó ṣe ìlérí láti tẹ̀lé òfin àti ìlànà tó tọ́.

Oͅkan lara awoͅn ohun ti Kwankwaso soͅ pe oun yoo se ni lati fopin si igbesunmoͅmi ati eto aabo to meͅheͅ ni Naijiria.

Leͅyin to kuro ni isejoͅba tan lo pada si eto oselu ni ipinleͅ Kano, to si beͅreͅ igbimoͅ Kwankwasiyya movement, eleyii to se ni ateͅle ajijagbara loͅwoͅ awoͅn afinise owo eͅru nigba naa loͅhun, Malam Aminu Kano.

Awoͅn alaileͅyin reͅ yii ma n woͅ fila pupa peͅlu asͅoͅ fufu , ti o si ma n fi aidoͅgba han ni awujoͅ, paapaa ai kii bu oͅla fun awoͅn obinrin ni awujoͅ woͅn

Kwankwaso ni gbogbo awoͅn ileri yii ni oun musͅeͅ lasiko ti oun w ani ipo gomina ni Kano, paapaa eto eͅkoͅ to muna doko.

O mu eto eͅkoͅ deͅrun fun awoͅn ara ilu nipa ipese eto eͅkoͅ oͅfeͅ fun awoͅn araalu.

Amoͅ, awoͅn oͅmoͅ bibi ipinleͅ Kano nikan ni anfaani yii wa fun nitori woͅn yoo safihan sabuke to soͅ wi pe ipinleͅ Kano ni woͅn ti wa, ki woͅn to le jeͅ ere eto eͅkoͅ oͅfeͅ.

''Kete to de ipo gomina lo kede eto oͅfeͅ fun awoͅn araalu, to si beͅreͅ si ni fun awoͅn oͅmo ileeͅkoͅ ni ounjeͅ oͅfeͅ.

Ninu oͅroͅ reͅ, Kwankwaso ni eto eͅkoͅ jeͅ oun lokun nitori o poͅn dandan fun awoͅn oͅmoͅ lati loͅ si ileeͅkoͅ

Eyi ko sͅeͅyin bi oun fun ara reͅ se pegede ninu eto eͅkoͅ to si loͅ si fasiti, to si tun keͅkoͅ imoͅ onimoͅ eͅroͅ lori omi ni Ileͅ Geͅeͅsi to fi moͅ India.

O pada si enu isͅeͅ ni eͅka naa ni ipinleͅ Kano, ki o to wo inu eto oselu loͅ ni Naijiria.

Eͅsun lilu owo ifeͅyinti awoͅn araalu ni ponpo

Bi awoͅn oloselu miran ni Naijiria, woͅn ti fi eͅsun jeͅgudujeͅra kan Kwankwaso.

Ni oͅdun 2021 leͅyin o pari saa reͅ geͅgeͅ bi seͅnetoͅ ni ajoͅ EFCC pe lori ͅeͅsun pe o lu owo ifeͅyinti awoͅn araalu ni ponpo lasiko to w ani ipo gomina.

Amoͅ Kwankwaso ni ko si otitoͅ ninu eͅsun naa ati pe awoͅn oͅbayejeͅ ninu oselu ni woͅn feͅ ba orukoͅ oun jeͅ, ti eͅsun naa si pari sibeͅ.

Kwankwaso to ti feͅ iyawo to si bi oͅmoͅ meͅfa ni iseͅ oselu ye oun yekeyeke.

O jeͅ eniyan to feͅran lati maa ni ipa rere lai teͅle eͅnikeͅni, oun lo jeͅ ki aworan reͅ kaakiri gbogbo ipinleͅ Kano.

Bakan naa ni orukoͅ reͅ , Kwankwasiyaa wa lara gbogbo awoͅn ile nla nla to koͅ si ipinleͅ Kano lasiko ijoͅba rͅ, to si ni pe oun ko feͅ ki eͅnikeͅni gbagbe oun.