Baba Suwe: Suwebatu sọ ìdí tí wọn kò fi sin olóògbé ní kété tó kú

Eto isinku Baba Suwe ti waye nile rẹ to wa nilu Ikorodu nibi ti tẹbi tara ati awọn akẹẹgbẹ rẹ peju si.
Ilana ẹsin Islam ni wọn fi sin gbajumọ alawada naa eyi ti awọn agbaagba ninu ẹsin Islam dari rẹ.
Amọ ohun to n ya ọpọ eeyan lẹnu nipa ilana isinku Baba Suwe naa ni bi wọn se gbe oku rẹ sinu posi olowo iyebiye wa sile rẹ.
- Ẹ wo ẹni tó ń jẹ́ Suwebatu nínú ẹbí Baba Suwe àti ohun tó sọ nípa olóògbé
- Bí ètò ìsìnkú Baba Suwe yóò ṣe lọ rèé, bó ṣe ń wọ ilẹ̀ sùn lónìí
- Mọ̀ si nípa ìtàn ayé Baba Suwe tó ń wọ káà ilẹ̀ sún lónìí
- Bàbá mi máa ń sunkún torí bí kò ṣe le padà ṣeré tíátà mọ́ - Ọmọ Baba Suwe
- Awuyewuye súyọ lórí fídíò òkú Baba Suwe tó lu ayelujára pa
- Wo nǹkan mẹ́jọ tí o lè má mọ̀ nípa Baba Suwe tó dolóògbé
Posi naa si ni wọn gbe sori tabili kan, ti wọn si siju oku rẹ silẹ nibi ti wọn tẹ ni itẹ ẹyẹ si.
Awọn olorin Brigade si n kọrin fun awọn eeyan lati se ẹyẹ fun oloogbe, gẹgẹ bi awọn onigbagbọ ti maa n se.

Amọ ọpọ eeyan lo n beere pe ki lo de ti wọn gbe oku oloogbe naa sinu posi nigba to jẹ pe ilana musulumi ni wọn fẹ sin.
Gẹgẹ ba se mọ pe patako gbọọrọ ni wọn maa n fi gbe oku musulumi, ti wọn kii si fi posi sin wọn.
Awọn ọmọ, ẹbi ati akẹẹgbẹ Baba Suwe lo fẹ ki wọn fi posi sin:
Aya akọfẹ Baba Suwe, Ayọdele, ti oun naa si jẹ osere tiata, ti ọpọ eeyan mọ si Suwebatu salaye fun BBC Yoruba idi ti eyi fi ri bẹẹ.
Ayodele ni lootọ ni awọn fẹ fi posi sin ọkọ oun, Baba Suwe, bi o tilẹ jẹ pe musulumi ni ko to jade laye.
"Posi la fẹ fi sin Baba Suwe, bi awọn ọmọ ati ẹbi rẹ se fẹ niyẹn.
Olorukọ ati olokiki ni Baba Suwe, awọn ọmọ ati ẹbi ko si fẹ ki wọn sin bii aja.
Idi ree ta se fẹ se ẹyẹ nla fun gẹgẹ bii eeyan pataki to jẹ ni awujọ."
Alaye ree ti a ko fi sin Baba Suwe ni kete to ku:
Nigba to n salaye idi ti wọn ko se sin Baba Suwe ni kete to ku, ti wọn si fi ọjọ mẹta silẹ lẹyin to ku, ki wọn to sin.
Aya akọfẹ oloogbe naa ni ọmọ oloogbe meji lo wa lẹyin odi, ti wọn si nilo akoko diẹ ki wọn to de lati wa se ẹyẹ ikẹyin fun baba wọn to lọ.
Idi si ree ti wọn ko fi le sin oloogbe naa ni kete to ku gẹgẹ bi ẹlẹsin Islam.
Ayodele ni Baba Suwe bi ọkunrin ati obinrin, ti oun pẹlu Moladun, to jẹ osere tiata ati awọn mii si bimọ fun.
O ni itọju gbogbo wọn si wa lọwọ oun bayii, bẹẹ lo n rawọ ẹbẹ si Ọba Oke pe ko ba oun tọju gbogbo wọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Lẹ́yìn ti mo lo ọdún 42 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, wọ́n tú mi sílẹ̀ pé ń kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn"
- Èròngbà ìjọba Naijiria lórí yíyọ 'subsidy' rújú, a kò fara mọ̀-NLC
- Clem Ohameze, òṣèré tíátà ní àìlera, ó ń bẹ̀bẹ̀ àdúrà lórí iṣẹ́ abẹ
- N kò rán ẹnikẹ́ni láti pín ìrẹ̀sì àti ẹ̀wà tórí ìbò ààrẹ 2023 - Bola Tinubu figbe ta
- Ẹ màá múra sílẹ̀ láti ra lítà epo kan ní ₦320 sí ₦340 lọ́dún 2022- NNPC
- Tówẹ́ẹ̀lì ni bàbá mi ró mọ́ ìdí nígbà tí àwọn sọ́jà wọlé mu lọ - Ọmọ Akintunde
- Jàndùkú kọlù mi, gé mi lára bíi olè torí mo jẹ́rìí tako ìjọba níbi ìwádìí ìpànìyàn Endsars Lekki''
- Femi Fani-Kayode ṣàlàyé bí ìrìnàjò rẹ̀ sọ́dọ̀ EFCC ṣe jẹ́
- Ẹ lọ san ₦20bn owó ìtanràn fún Sunday Igboho títí January - Iléejọ́ fọnmú fún DSS
Ẹba saare Omoladun ni wọn sin Baba Suwe si:
Bakan naa ni aya akọfẹ Baba Suwe tun salaye lori saare to wa lẹba ibi ti wọn sin ọkọ rẹ si.
Ayodele ni saare osere tiata mii to jẹ aya Baba Suwe, eyiun Omoladun ni iboji naa.
O ni Omoladun bimọ fun Baba Suwe, awọn mejeeji si ti fi iku se agba, idi ree tawọn se n sin wọn papọ.

Bí ètò ìsìnkú Baba Suwe yóò ṣe lọ rèé, bó ṣe ń wọ ilẹ̀ sùn lónìí

Oríṣun àwòrán, Omidina Family
Yoruba ni awaye ku ko si, ko si ẹni ti ko ni ku, ko si si ẹni ti oko baba rẹ ko ni di igboro.
Bo se ri gan ree fun gbajumọ osere tiata to jade laye, Babatunde Omidina ti ọpọ eeyan mọ si Baba Suwe.
Ọjọ Aje, ọjọ Kejilelogun, osu Kọkanla, ọdun 2021 ni Baba Suwe dagbere faye lasiko aisan ọlọjọ pipẹ lẹni ọdun mẹtalelọgọta.
Nibayii na, awọn ẹbi oloogbe ti fi ikede sita lori bi eto isinku Baba Suwe yoo se lọ ni Ọjọbọ, ọjọ Kẹẹdọgbọn osu Kọkanla ọdun 2021.
Atẹjade kan ti ọmọ oloogbe, Adesola Omidina fisita loju opo Instagram rẹ ni oni Ọjọbọ ni wọn yoo gbe oku oloogbe naa wọ kaa ilẹ nilana ẹsin Islam.

Oríṣun àwòrán, omo_omidina/Instagram
Atẹjade naa ni ile oloogbe to wa ojule Kẹrindinlgbọn, opopona Oluwatimiro, ibudokọ Ewu-Elepe, ni opopona Ijede nilu Ikorodu, ni wọn yoo ti sin Baba Suwe.
Deede aago mẹwa owurọ ni eto isinku naa yoo bẹrẹ́
Adesola Omidina ni awọn mọlẹbi oloogbe yoo kede ayẹyẹ isinku nigba to ba ya.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Lẹ́yìn ti mo lo ọdún 42 lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, wọ́n tú mi sílẹ̀ pé ń kò jẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn"
- Malawi kọ lẹ́tà sí Mike Tyson pé kó di asojú wọn fún ewé ọlà, igbó
- Èèmọ̀! Bíṣọ́ọ́bù bá ọmọ tuntun lórí pẹpẹ ṣọ́ọ̀ṣì, láì mọ ẹni tó ni
- Àlàyé ọlọ́pàá Osun rèé lórí ọ̀nà tí Rahmon Adedoyin gbà ká ọ̀rọ̀ rẹ̀ sínu fọ́nrán ohùn tó lu ayélujára pa
- "Akẹ́kọ̀ọ́ 1,440 ní iléẹ̀kọ́ 25 ni àwọn agbébọn ti jígbè lọ ní Naijiria"
- Àwọn ọlọ́pàá ti ń wá okùnrin tó gbé òkú ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ sínú fííjì lẹ́yìn tó gbẹ̀mí rẹ̀ tán
Bi gbogbo eto isinku Baba Suwe ba si se n lọ, nileesẹ BBC Yoruba yoo maa mu wa fun yin, ẹ ku oju lọna.
Ọjọ Aje, ọjọ Kejilelogun osu Kọkanla ọdun 2021 ni agba osere tiata naa, tii tun se adẹrinposonu ti ọpọ eeyan mọ si Baba Suwe ki aye pe o digbose.
Ọdun mẹtalelọgọta ni alawada naa lo loke eepẹ, ko to dagbere faye lasiko aisan ọlọjọ pipẹ to ba finra.




















